< Revelation 4 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí èmi wò, sì kíyèsi i, ìlẹ̀kùn kan ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run, ohùn kìn-ín-ní tí mo gbọ́ bí ohùn ìpè tí ń bá mi sọ̀rọ̀, tí ó wí pé, “Gòkè wá níhìn-ín, èmi ó sì fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn èyí hàn ọ́.”
MAHOPE iho o keia mau mea, nana aku la au, aia hoi, he puka e hamama ana maloko o ka lani; a o ka leo mua a'u i lohe ai, ua like ia me ko ka pu e kamailio ana ia'u, i mai la, E pii mai oe ia nei, a na'u no e hoike aku ia oe i na mea e hiki mai ana ma keia hope aku.
2 Lójúkan náà, mo sì wà nínú Ẹ̀mí, sì kíyèsi i, a tẹ́ ìtẹ́ kan ní ọ̀run, ẹnìkan sì jókòó lórí ìtẹ́ náà.
Hihio koke iho la au i ka Uhane; aia hoi, ua hoonohoia he nohoalii ma ka lani, a he mea hoi e noho ana maluna o ua nohoalii la.
3 Ẹni tí ó sì jókòó náà dàbí òkúta jasperi àti kaneliani lójú. Ni àyíká ìtẹ́ náà ni òṣùmàrè kan wà tí ó dàbí òkúta emeradi lójú.
A o ka mea e noho ana, ua like kona helehelena, me ka pohaku Iasepi a me ka Saredio; a he anuenue i pio mai la a puni ka nohoalii, me he pohaku omaomao la.
4 Yí ìtẹ́ náà ká sì ni ìtẹ́ mẹ́rìnlélógún mìíràn; àti lórí àwọn ìtẹ́ náà mo rí àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún jókòó, tí a wọ̀ ni aṣọ àlà; adé wúrà sì wà ni orí wọn.
Ua puni kela nohoalii i na noho he iwakaluakumamaha; a maluna iho o ua poe noho la, e noho ana he poe lunakahiko, he iwakaluakumamaha, ua aahuia i ka aahu keoheo; a maluna iho o ko lakou mau poo, he mau leialii gula.
5 Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni ìró mọ̀nàmọ́ná àti ohùn àti àrá ti jáde wá: níwájú ìtẹ́ náà ni fìtílà iná méje sì ń tàn, èyí tí ń ṣe Ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run.
Anapu mai la ka uila mai ka nohoalii mai, a me ka hekili, a me na leo. Ehiku hoi ipukukui ahi e aa ana imua o ka nohoalii, oia hoi na Uhane ehiku o ke Akua.
6 Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni òkun bi dígí wà tí o dàbí kristali. Àti yí ìtẹ́ náà ká ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí ó kún fún ojú níwájú àti lẹ́yìn wọn.
Aia hoi, imua o ka nohoalii, he moana akaka, me he aniani la; a ma ka nohoalii, a puni hoi ka nohoalii, eha mau mea ola, ua paapu i na maka mamua a mahope.
7 Ẹ̀dá kìn-ín-ní sì dàbí kìnnìún, ẹ̀dá kejì si dàbí ọmọ màlúù, ẹ̀dá kẹta sì ni ojú bi ti ènìyàn, ẹ̀dá kẹrin sì dàbí idì tí ń fò.
A o ka mua o ka mea ola, ua like ia me ka liona; a o ka lua o ka mea ola ua like ia me ke keiki bipi, a o ke kolu o ka mea ola, ua like kona maka me ko ke kanaka, a o ka ha o ka mea ola, ua like ia me ka aeto lele.
8 Àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà, tí olúkúlùkù wọn ni ìyẹ́ mẹ́fà, kún fún ojú yíká ara àti nínú; wọn kò sì sinmi lọ́sàn àti lóru, láti wí pé:
A o ua poe mea ola la eha, ua papa ono lakou i na eheu; ua paapu i na maka a puni a maloko; aole hoi lakou i hoomaha i ke ao a me ka po, i ka i ana mai, Hoano, Hoano, Hoano, ka Haku ke Akua mana loa, ka mea mamua, ka mea e noho la, ka mea e noho la, ka mea e mau loa ana.
9 Nígbà tí àwọn ẹ̀dá alààyè náà bá sì fi ògo àti ọlá, àti ọpẹ́ fún ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, tí o ń bẹ láààyè láé àti láéláé. (aiōn )
A i ka wa e hoomana aku ai, a i hoonani aku ai, a hoomaikai aku ai na mea ola i ka mea e noho ana ma ka nohoalii, oia hoi ka Mea e ola mau ana ia ao aku ia ao aku, (aiōn )
10 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà yóò sì wólẹ̀ níwájú ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, wọn yóò sì tẹríba fún ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé, wọn yóò sì fi adé wọn lélẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà, wí pé: (aiōn )
Alaila, moe iho la ka poe lunakahiko he iwakaluakumamaha, imua o ka mea e noho ana ma ka nohoalii, a hoomana aku la i ka mea e ola mau ana ia ao aku, ia ao aku; a hoolei no hoi i ko lakou mau leialii imua o ka nohoalii, me ka i ana ae, (aiōn )
11 “Olúwa àti Ọlọ́run, ìwọ ni o yẹ, láti gba ògo àti ọlá àti agbára, nítorí pé ìwọ ni o dá ohun gbogbo, àti nítorí ìfẹ́ inú rẹ̀ ni wọn fi wà tí a sì dá wọn.”
E pono no oe, e ka Haku, ke loaa ia oe ka nani a me ka mahalo a me ka mana; no ka mea, nau no i hana i na mea a pau, a ma kou makemake no lakou i mau ai a hanaia hoi.