< Revelation 4 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí èmi wò, sì kíyèsi i, ìlẹ̀kùn kan ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run, ohùn kìn-ín-ní tí mo gbọ́ bí ohùn ìpè tí ń bá mi sọ̀rọ̀, tí ó wí pé, “Gòkè wá níhìn-ín, èmi ó sì fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn èyí hàn ọ́.”
ⲁ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲓⲛⲁⲩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲟⲩⲣⲟ ⲉϥⲟⲩⲏⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲟⲩⲟϩ ϯ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲛϩⲟⲩⲓϯ ⳿ⲉⲛⲁⲥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⲑⲏ ⲉⲧⲁⲓⲥⲟⲑⲙⲉⲥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛ⳿ⲧ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲁⲗⲡⲓⲅⲝ ⲉⲥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⲉⲥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲙⲛⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲁⲧⲁⲙⲟⲕ ⳿ⲉⲛⲏⲉⲑⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ.
2 Lójúkan náà, mo sì wà nínú Ẹ̀mí, sì kíyèsi i, a tẹ́ ìtẹ́ kan ní ọ̀run, ẹnìkan sì jókòó lórí ìtẹ́ náà.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓⲛⲁⲩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲟⲩ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉϥϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ.
3 Ẹni tí ó sì jókòó náà dàbí òkúta jasperi àti kaneliani lójú. Ni àyíká ìtẹ́ náà ni òṣùmàrè kan wà tí ó dàbí òkúta emeradi lójú.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓ ⳿ⲡ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲛⲁϥⲟⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲡⲉ ⳿ⲛⲓⲁⲥⲡⲓⲥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲁⲣⲇⲓⲛⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ϯ⳿ⲓⲣⲓⲥ ⲉⲥⲕⲱϯ ⳿ⲉⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⳿ⲛ⳿ⲥⲙⲁⲣⲁⲕⲇⲟⲥ.
4 Yí ìtẹ́ náà ká sì ni ìtẹ́ mẹ́rìnlélógún mìíràn; àti lórí àwọn ìtẹ́ náà mo rí àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún jókòó, tí a wọ̀ ni aṣọ àlà; adé wúrà sì wà ni orí wọn.
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲕ̅ⲇ̅ ⳿ⲛ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉⲩⲭⲏ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲱϯ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲕ̅ⲇ̅ ⳿ⲙ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ ⲉⲩϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉⲩ⳿ⲕⲧⲏⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϭⲓ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲃϣ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲭⲗⲟⲙ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲃ ⲉⲩⲧⲟⲓ ⳿ⲉⲛⲟⲩ⳿ⲁⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ.
5 Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni ìró mọ̀nàmọ́ná àti ohùn àti àrá ti jáde wá: níwájú ìtẹ́ náà ni fìtílà iná méje sì ń tàn, èyí tí ń ṣe Ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run.
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲥⲉⲧⲉⲃⲣⲏϫ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲥⲙⲏ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϧⲁⲣⲁⲃⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲍ̅ ⳿ⲛⲗⲁⲙⲡⲁⲥ ⳿ⲛ⳿ⲭⲣⲱⲙ ⲉⲩⲕⲱϯ ⳿ⲉⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲍ̅ ⳿ⲙⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲛⲉ.
6 Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni òkun bi dígí wà tí o dàbí kristali. Àti yí ìtẹ́ náà ká ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí ó kún fún ojú níwájú àti lẹ́yìn wọn.
ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲭⲏ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲓⲟⲙ ⳿ⲙⲃⲁϫⲏⲓⲛⲓ ⲉϥ⳿ⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲭⲣⲓⲥⲧⲁⲗⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲏϯ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲇ̅ ⳿ⲛⲍⲱⲟⲛ ⲉⲩⲙⲉϩ ⳿ⲙⲃⲁⲗ ϩⲓ⳿ⲧϩⲏ ⲛⲉⲙ ϩⲓⲫⲁϩⲟⲩ.
7 Ẹ̀dá kìn-ín-ní sì dàbí kìnnìún, ẹ̀dá kejì si dàbí ọmọ màlúù, ẹ̀dá kẹta sì ni ojú bi ti ènìyàn, ẹ̀dá kẹrin sì dàbí idì tí ń fò.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲍⲱⲟⲛ ⳿ⲛϩⲟⲩⲓⲧ ⲉϥⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲟⲩ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲍⲱⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲁϩⲃ̅ ⲉϥⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲁⲥⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲍⲱⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲁϩⲅ̅ ⲉϥⲟⲛⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲟ ⳿ⲛⲟⲩϣⲏ ⲣⲓ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲍⲱⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲁϩⲇ̅ ⲉϥⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲁϧⲱⲙ ⲉϥϩⲏⲗ.
8 Àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà, tí olúkúlùkù wọn ni ìyẹ́ mẹ́fà, kún fún ojú yíká ara àti nínú; wọn kò sì sinmi lọ́sàn àti lóru, láti wí pé:
ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲩⲕⲱϯ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲛⲟⲩⲓⲉⲃ ⲥⲁϧⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲩⲙⲉϩ ⳿ⲙⲃⲁⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲙⲟⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⲛⲉ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ϥⲟⲩⲁⲃ ⳿ϥⲟⲩⲁⲃ ⳿ϥⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡ⳪ ⲫϯ ⲡⲓⲡⲁⲛⲧⲟⲕⲣⲁⲧⲱⲣ ⲫⲏⲉⲧϣⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏ ⳿ⲉⲛⲁϥϣⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ.
9 Nígbà tí àwọn ẹ̀dá alààyè náà bá sì fi ògo àti ọlá, àti ọpẹ́ fún ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, tí o ń bẹ láààyè láé àti láéláé. (aiōn g165)
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲡⲓⲇ̅ ⳿ⲛⲍⲱⲟⲛ ϯ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲁⲓⲧⲁⲓⲟ ⲛⲉⲙ ⲡⲁⲓϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲫⲏⲉⲧⲟⲛϧ ϣⲁ ⲉⲛⲉϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲛⲉϩ. (aiōn g165)
10 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà yóò sì wólẹ̀ níwájú ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, wọn yóò sì tẹríba fún ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé, wọn yóò sì fi adé wọn lélẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà, wí pé: (aiōn g165)
ⲓ̅ϣⲁⲩϩⲓⲧⲟⲩ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲟⲩϩⲟ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲕ̅ⲇ̅ ⳿ⲙ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲩⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲟⲛϧ ϣⲁ ⲉⲛⲉϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲛⲉϩ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲩⲭⲱ ⳿ⲛⲛⲟⲩ⳿ⲭⲗⲟⲙ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ. (aiōn g165)
11 “Olúwa àti Ọlọ́run, ìwọ ni o yẹ, láti gba ògo àti ọlá àti agbára, nítorí pé ìwọ ni o dá ohun gbogbo, àti nítorí ìfẹ́ inú rẹ̀ ni wọn fi wà tí a sì dá wọn.”
ⲓ̅ⲁ̅ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲉⲧⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ Ⲡ⳪ ⲡⲉⲛⲛⲟⲩϯ ⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲧⲁⲓⲟ ⲛⲉⲙ ϯϫⲟⲙ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲁⲕⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁⲕ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲥⲱⲛⲧ

< Revelation 4 >