< Revelation 3 >
1 “Àti sí angẹli ìjọ ni Sardi kọ̀wé: Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ni Ẹ̀mí méje Ọlọ́run, àti ìràwọ̀ méje wí pé. Èmi mọ iṣẹ́ rẹ̀, àti pé ìwọ ní orúkọ pé ìwọ ń bẹ láààyè, ṣùgbọ́n ìwọ ti kú.
Aniołowi kościoła w Sardes napisz tak: To mówi Ten, który ma siedem Bożych Duchów i siedem gwiazd. Znam twoje czyny. Nosisz imię świadczące o tym, że żyjesz, ale jesteś martwy.
2 Jí, kí o sì fi ẹsẹ̀ ohun tí ó kù múlẹ̀, tàbí tí ó ṣetán láti kú, nítorí èmi kò rí iṣẹ́ rẹ ni pípé níwájú Ọlọ́run.
Dlatego uważaj na siebie! Zadbaj też o tych, którzy pozostali przy życiu, ale są już bliscy śmierci! Twoje czyny są w oczach Boga dalekie od doskonałości.
3 Nítorí náà rántí bí ìwọ ti gbà, àti bí ìwọ ti gbọ́, kí o sì pa á mọ́, kí o sì ronúpìwàdà. Ǹjẹ́, bí ìwọ kò ba ṣọ́ra, èmi yóò dé sí ọ bí olè, ìwọ kì yóò sì mọ́ wákàtí tí èmi yóò dé sí ọ.
Wróć więc do nauki, którą przyjąłeś na początku! Uchwyć się jej i opamiętaj się! Jeśli nie posłuchasz, zjawię się nieoczekiwanie jak złodziej i nie zorientujesz się, kiedy nadejdę!
4 Ìwọ ní orúkọ díẹ̀ ní Sardi, tí kò fi aṣọ wọn yí èérí; wọn yóò sì máa ba mi rìn ní aṣọ funfun: nítorí wọ́n yẹ.
Masz jednak w Sardes kilku ludzi, którzy nie pobrudzili swoich szat. Będą oni chodzić razem ze Mną w białych szatach, gdyż są tego godni.
5 Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun, òun náà ni a ó fi aṣọ funfun wọ̀; èmi kì yóò pa orúkọ rẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, ṣùgbọ́n èmi yóò jẹ́wọ́ orúkọ rẹ̀ níwájú Baba mi, àti níwájú àwọn angẹli rẹ̀.
Zwycięzcy dam białe szaty i nie usunę jego imienia z księgi życia, ale przyznam się do niego wobec Ojca i Jego aniołów.
6 Ẹni tí ó ba létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
Kto ma uszy do słuchania, niech uważnie słucha tego, co Duch mówi do kościołów!
7 “Àti sí angẹli Ìjọ ni Filadelfia kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ náà wí, ẹni tí ó ṣe olóòtítọ́, ẹni tí ó ní kọ́kọ́rọ́ Dafidi, ẹni tí ó ṣí, tí kò sí ẹni tí yóò tì; ẹni tí o sì tì, tí kò sì ẹni tí yóò ṣí i.
Aniołowi kościoła w Filadelfii napisz tak: To mówi Święty i Prawdziwy, który posiada klucz króla Dawida: jeśli otworzy drzwi, nikt nie może zamknąć; a jeśli je zamknie, nikt nie może ich otworzyć.
8 Èmi mọ iṣẹ́ rẹ̀, kíyèsi i, mo gbe ìlẹ̀kùn tí ó ṣí kálẹ̀ níwájú rẹ̀, tí kò sí ẹni tí o lè tì í; pé ìwọ ni agbára díẹ̀, ìwọ sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, ìwọ kò sì sẹ́ orúkọ mi.
Znam twoje czyny. Wiem, że nie posiadasz wielkiej mocy, a jednak trzymałeś się mojego słowa i nie zaparłeś się Mnie. Dlatego otworzyłem przed tobą drzwi, których nikt nie może zamknąć.
9 Kíyèsi i, èmi ó mú àwọn ti Sinagọgu Satani, àwọn tí wọ́n ń wí pé Júù ni àwọn, tí wọn kì í sì ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọn ń ṣèké; kíyèsi i, èmi ó mú kí wọn wá wólẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ rẹ̀, kí wọn sì mọ̀ pé èmi tí fẹ́ ọ.
Sprawię, że ci, którzy podają się za pobożnych Żydów, choć w rzeczywistości należą do szatana, przyjdą i padną u twoich stóp, i zrozumieją, że cię kocham.
10 Nítorí tí ìwọ tí pa ọ̀rọ̀ sùúrù mi mọ́, èmi pẹ̀lú yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú wákàtí ìdánwò, tí ń bọ̀ wá dé bá gbogbo ayé, láti dán àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé wò.
Ponieważ wytrwale trzymałeś się mojego słowa, ochronię cię w czasie próby, której poddany zostanie cały świat i wszyscy jego mieszkańcy.
11 Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán, di èyí ti ìwọ ní mú ṣinṣin, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gba adé rẹ.
Już wkrótce powrócę! Pilnuj więc tego, co masz, aby nikt nie odebrał ci czekającego na ciebie wieńca.
12 Ẹni tí ó ba ṣẹ́gun, òun ni èmi ó fi ṣe ọ̀wọ́n nínú tẹmpili Ọlọ́run mi, òun kì yóò sì jáde kúrò níbẹ̀ mọ́, èmi ó sì kọ orúkọ Ọlọ́run mi sí i lára, àti orúkọ ìlú Ọlọ́run mi, tí i ṣe Jerusalẹmu tuntun, tí ó ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi wá: àti orúkọ tuntun ti èmi tìkára mi.
Zwycięzcę uczynię filarem w świątyni mojego Boga i nikt nie będzie w stanie go z niej usunąć. Wypiszę na nim imię mojego Boga oraz nazwę Jego miasta—nowej Jerozolimy, zstępującej z nieba, od mojego Boga. Wypiszę na nim również moje nowe imię!
13 Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́ ohun ti Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
Kto ma uszy do słuchania, niech uważnie słucha tego, co Duch mówi do kościołów!
14 “Àti sí angẹli ìjọ ní Laodikea kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ń jẹ́ Àmín wí, ẹlẹ́rìí olódodo àti olóòtítọ́, olórí ìṣẹ̀dá Ọlọ́run.
Aniołowi kościoła w Laodycei napisz tak: To mówi Amen, wierny i prawdziwy świadek, źródło Bożego stworzenia.
15 Èmi mọ̀ iṣẹ́ rẹ, pé ìwọ kò gbóná bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò tútù: èmi ìbá fẹ́ pé kí ìwọ kúkú tutù, tàbí kí ìwọ kúkú gbóná.
Znam twoje czyny. Nie jesteś ani zimny, ani gorący. Obyś się zdecydował!
16 Ǹjẹ́ nítorí tí ìwọ lọ wọ́ọ́rọ́, tí o kò si gbóná, bẹ́ẹ̀ ni tí o kò tutù, èmi yóò pọ̀ ọ́ jáde kúrò ni ẹnu mi.
Skoro jednak jesteś tylko letni—ani zimny, ani gorący—wypluję cię z moich ust.
17 Nítorí tí ìwọ wí pé, èmi ní ọrọ̀, èmi sì ń pọ̀ sí i ni ọrọ̀, èmi kò sì ṣe aláìní ohunkóhun; tí ìwọ kò sì mọ̀ pé, òsì ni ìwọ, ẹni-ìkáàánú, tálákà, afọ́jú, àti ẹni ìhòhò:
Mówisz: „Jestem bogaty, wszystko mam i niczego mi nie brakuje”. Nie zdajesz sobie jednak sprawy z tego, że tak naprawdę jesteś godnym pożałowania nędzarzem—biednym, ślepym i nagim.
18 Èmi fún ọ ni ìmọ̀ràn pé kí o ra wúrà lọ́wọ́ mi tí a ti dà nínú iná, kí ìwọ lè di ọlọ́rọ̀; àti aṣọ funfun, kí ìwọ lè fi wọ ara rẹ̀, àti kí ìtìjú ìhòhò rẹ̀ má ba hàn kí ìwọ sì fi ohun ìkunra kun ojú rẹ̀, kí ìwọ lè ríran.
Radzę ci więc kupić ode Mnie złoto, które zostało oczyszczone w ogniu, a wtedy naprawdę staniesz się bogaty. Kup ode Mnie również białą szatę, abyś mógł się nią okryć i byś nie musiał wstydzić się swojej nagości. Kup także maść do oczu, abyś przejrzał.
19 Gbogbo àwọn ti èmi bá fẹ́ ni èmi ń bá wí, tí mo sì ń nà: nítorí náà, ní ìtara, kì ìwọ sì ronúpìwàdà.
Wszystkich, których kocham, upominam i karzę. Bądź gorliwy i opamiętaj się!
20 Kíyèsi i, èmi dúró ni ẹnu ìlẹ̀kùn, èmi sì ń kànkùn, bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ohun mi, tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn, èmi yóò sì wọlé tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bá a jẹun, àti òun pẹ̀lú mi.
Oto stanąłem przed drzwiami i pukam. Jeśli ktoś usłyszy mój głos i otworzy drzwi, wejdę do niego i będziemy razem ucztować: Ja z nim, a on ze Mną.
21 Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi fún láti jókòó pẹ̀lú mi lórí ìtẹ́ mi, bí èmi pẹ̀lú ti ṣẹ́gun, tí mo sì jókòó pẹ̀lú Baba mi lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Zwycięzcy pozwolę zasiąść razem ze Mną na moim tronie—Ja również jako zwycięzca zasiadłem z Ojcem na Jego tronie.
22 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.”
Kto ma uszy do słuchania, niech uważnie słucha tego, co Duch mówi do kościołów!