< Revelation 3 >

1 “Àti sí angẹli ìjọ ni Sardi kọ̀wé: Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ni Ẹ̀mí méje Ọlọ́run, àti ìràwọ̀ méje wí pé. Èmi mọ iṣẹ́ rẹ̀, àti pé ìwọ ní orúkọ pé ìwọ ń bẹ láààyè, ṣùgbọ́n ìwọ ti kú.
ⲁ̅⳿ⲥϧⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲥⲁⲣⲇⲓⲥ ϫⲉ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲡⲓⲍ̅ ⳿ⲙⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲭⲏ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲍ̅ ⳿ⲛⲥⲓⲟⲩ ϫⲉ ϯⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲛⲉⲕ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲁⲕ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲟⲩϫⲁⲓ ϫⲉ ⳿ⲕⲟⲛϧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲕⲙⲱⲟⲩⲧ.
2 Jí, kí o sì fi ẹsẹ̀ ohun tí ó kù múlẹ̀, tàbí tí ó ṣetán láti kú, nítorí èmi kò rí iṣẹ́ rẹ ni pípé níwájú Ọlọ́run.
ⲃ̅ϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲛ ⲉⲕⲣⲏⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲁⲧⲁϫⲣⲉ ⳿ⲡⲥⲉⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲭⲛⲁⲙⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲓϫⲉⲙ ⲛⲉⲕ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲉⲩϫⲏⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲡⲁⲛⲟⲩϯ.
3 Nítorí náà rántí bí ìwọ ti gbà, àti bí ìwọ ti gbọ́, kí o sì pa á mọ́, kí o sì ronúpìwàdà. Ǹjẹ́, bí ìwọ kò ba ṣọ́ra, èmi yóò dé sí ọ bí olè, ìwọ kì yóò sì mọ́ wákàtí tí èmi yóò dé sí ọ.
ⲅ̅ⲁⲣⲓ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⲁⲕϭⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲕⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲉϩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲓⲙⲉⲧⲁⲛⲟⲓⲛ ⲉϣⲱⲡ ⲟⲩⲟⲛ ⲁⲕ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣⲙⲉⲧⲁⲛⲟⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲕ⳿ϣⲧⲉⲙⲣⲱⲓⲥ ϯⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲉϥϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲭⲛⲁ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉϯⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉϫⲱⲕ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
4 Ìwọ ní orúkọ díẹ̀ ní Sardi, tí kò fi aṣọ wọn yí èérí; wọn yóò sì máa ba mi rìn ní aṣọ funfun: nítorí wọ́n yẹ.
ⲇ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛⲣⲁⲛ ⳿ⲛⲧⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲥⲁⲣⲇⲓⲥ ⲛⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲑⲱⲗⲉⲃ ⳿ⲛⲛⲟⲩ⳿ϩⲃⲱⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ⲉⲙⲟϣⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲃϣ ϫⲉ ⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⲅⲁⲣ.
5 Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun, òun náà ni a ó fi aṣọ funfun wọ̀; èmi kì yóò pa orúkọ rẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, ṣùgbọ́n èmi yóò jẹ́wọ́ orúkọ rẹ̀ níwájú Baba mi, àti níwájú àwọn angẹli rẹ̀.
ⲉ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϭⲣⲟ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲉⲩ⳿ⲉϯ ϩⲓⲱⲧϥ ⳿ⲛϩⲁⲛϭⲓ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲃϣ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲥⲉⲗϫ ⲡⲟⲩⲣⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓ ⲡⲓϫⲱⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲛϧ ⲉⲓ⳿ⲉⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲣⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲉϥⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ.
6 Ẹni tí ó ba létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
ⲋ̅ⲫⲏⲉⲧ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲛⲓⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ.
7 “Àti sí angẹli Ìjọ ni Filadelfia kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ náà wí, ẹni tí ó ṣe olóòtítọ́, ẹni tí ó ní kọ́kọ́rọ́ Dafidi, ẹni tí ó ṣí, tí kò sí ẹni tí yóò tì; ẹni tí o sì tì, tí kò sì ẹni tí yóò ṣí i.
ⲍ̅⳿ⲥϧⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲓⲗⲁⲇⲉⲗⲫⲓⲁ ϫⲉ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲡⲓ⳿ⲑⲙⲏⲓ ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲛⲓϣⲟϣⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲛⲇⲁⲩⲓⲇ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲟⲩⲱⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⲛⲁ⳿ϣⲑⲁⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ϣⲑⲁⲙ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⲛⲁⲟⲩⲱⲛ.
8 Èmi mọ iṣẹ́ rẹ̀, kíyèsi i, mo gbe ìlẹ̀kùn tí ó ṣí kálẹ̀ níwájú rẹ̀, tí kò sí ẹni tí o lè tì í; pé ìwọ ni agbára díẹ̀, ìwọ sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, ìwọ kò sì sẹ́ orúkọ mi.
ⲏ̅ϯⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲛⲉⲕ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲕⲛⲁϩϯ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲁⲓϯ ⳿ⲙⲡⲉⲕ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟ ⲉϥ⳿ⲉⲟⲩⲏⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ϣⲑⲁⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲁⲕ ⳿ⲛⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲕ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲡⲁⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲕϫⲉⲗ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
9 Kíyèsi i, èmi ó mú àwọn ti Sinagọgu Satani, àwọn tí wọ́n ń wí pé Júù ni àwọn, tí wọn kì í sì ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọn ń ṣèké; kíyèsi i, èmi ó mú kí wọn wá wólẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ rẹ̀, kí wọn sì mọ̀ pé èmi tí fẹ́ ọ.
ⲑ̅ϩⲏⲡⲡⲉ ϯⲛⲁϯ ⲛⲁⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲥⲁⲧⲁⲛⲁⲥ ⲛⲏⲉⲧϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ϩⲁⲛⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲉ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲁⲛ ⲛⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲥⲉϫⲉⲙⲉⲑⲛⲟⲩϫ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲉⲓ⳿ⲉ⳿ⲑⲣⲟⲩ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲓ⳿ⲉ⳿ⲑⲣⲟⲩⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ⲉϩⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲉⲕϭⲁⲗⲁⲩϫ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲉ ⲉⲧⲁⲓⲙⲉⲛⲣⲓⲧⲕ.
10 Nítorí tí ìwọ tí pa ọ̀rọ̀ sùúrù mi mọ́, èmi pẹ̀lú yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú wákàtí ìdánwò, tí ń bọ̀ wá dé bá gbogbo ayé, láti dán àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé wò.
ⲓ̅ϫⲉ ⲁⲕ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲡⲁⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲧⲁϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ⲁⲓ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲣⲟⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲡⲓⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲑⲟ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ.
11 Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán, di èyí ti ìwọ ní mú ṣinṣin, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gba adé rẹ.
ⲓ̅ⲁ̅ϯⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲭⲱⲗⲉⲙ ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉ⳿ⲛⲧⲟⲧⲕ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ϭⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲕ⳿ⲭⲗⲟⲙ.
12 Ẹni tí ó ba ṣẹ́gun, òun ni èmi ó fi ṣe ọ̀wọ́n nínú tẹmpili Ọlọ́run mi, òun kì yóò sì jáde kúrò níbẹ̀ mọ́, èmi ó sì kọ orúkọ Ọlọ́run mi sí i lára, àti orúkọ ìlú Ọlọ́run mi, tí i ṣe Jerusalẹmu tuntun, tí ó ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi wá: àti orúkọ tuntun ti èmi tìkára mi.
ⲓ̅ⲃ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϭⲣⲟ ⲉⲓ⳿ⲉⲁⲓϥ ⳿ⲛ⳿ⲥⲧⲩⲗⲗⲟⲥ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲛⲟⲩϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲉϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲓ⳿ⲉ⳿ⲥϧⲉ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲛⲟⲩϯ ϩⲓⲱⲧϥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲛϯⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲙⲃⲉⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲑⲏ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲁⲛⲟⲩϯ ⲛⲉⲙ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲃⲉⲣⲓ.
13 Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́ ohun ti Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲛⲓⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ.
14 “Àti sí angẹli ìjọ ní Laodikea kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ń jẹ́ Àmín wí, ẹlẹ́rìí olódodo àti olóòtítọ́, olórí ìṣẹ̀dá Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲥϧⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲗⲁⲟⲇⲓⲕⲓⲁ ϫⲉ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲁⲙⲏⲛ ⲡⲓⲙⲁⲣⲧⲩⲣⲟⲥ ⲡⲓⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲁⲗⲏⲑⲓⲛⲟⲥ ⳿ⲧⲁⲣⲭⲏ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
15 Èmi mọ̀ iṣẹ́ rẹ, pé ìwọ kò gbóná bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò tútù: èmi ìbá fẹ́ pé kí ìwọ kúkú tutù, tàbí kí ìwọ kúkú gbóná.
ⲓ̅ⲉ̅ϯⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲛⲉⲕ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲕϩⲟⲣϣ ⲁⲛ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲕϧⲏⲙ ⲁⲛ ⳿ⲁⲙⲟⲓ ⲛⲁⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲩϩⲱϫ ⲡⲉ ⲓⲉ ⲛⲁⲕⲃⲉⲣⲃⲉⲣ.
16 Ǹjẹ́ nítorí tí ìwọ lọ wọ́ọ́rọ́, tí o kò si gbóná, bẹ́ẹ̀ ni tí o kò tutù, èmi yóò pọ̀ ọ́ jáde kúrò ni ẹnu mi.
ⲓ̅ⲋ̅ϫⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲩⲥⲉⲗϩⲟ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲩϧⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲩϩⲱϫ ⲁⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϯⲛⲁϣⲁⲧⲕ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⳿ϩⲑⲏⲓ.
17 Nítorí tí ìwọ wí pé, èmi ní ọrọ̀, èmi sì ń pọ̀ sí i ni ọrọ̀, èmi kò sì ṣe aláìní ohunkóhun; tí ìwọ kò sì mọ̀ pé, òsì ni ìwọ, ẹni-ìkáàánú, tálákà, afọ́jú, àti ẹni ìhòhò:
ⲓ̅ⲍ̅ϫⲉ ⳿ⲕϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⲟⲩⲟϩ ϯⲉⲣ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲕ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩϫⲱⲃ ⳿ⲛⲧⲁⲗⲉⲡⲱⲣⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩϣⲁⲧⲙⲉⲑⲛⲁⲓ ⳿ⲛϩⲏⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲃⲉⲗⲗⲉ ⲉⲕⲃⲏϣ.
18 Èmi fún ọ ni ìmọ̀ràn pé kí o ra wúrà lọ́wọ́ mi tí a ti dà nínú iná, kí ìwọ lè di ọlọ́rọ̀; àti aṣọ funfun, kí ìwọ lè fi wọ ara rẹ̀, àti kí ìtìjú ìhòhò rẹ̀ má ba hàn kí ìwọ sì fi ohun ìkunra kun ojú rẹ̀, kí ìwọ lè ríran.
ⲓ̅ⲏ̅ϯⲉⲣⲥⲩⲙⲃⲟⲩⲗⲉⲩⲓⲛ ⲛⲁⲕ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉϣⲉⲡ ⲟⲩⲛⲟⲩⲃ ⳿ⲛⲧⲟⲧ ⲉϥⲫⲟⲥⲓ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ ⳿ⲭⲣⲱⲙ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲕⲉⲣⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲱⲥ ⲉⲩⲫⲟⲣⲓ ⲙⲏⲓⲧⲟⲩ ϩⲓⲱⲧⲕ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡϣⲓⲡⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲕⲃⲱϣ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲕⲟⲩⲗⲁⲟⲩⲣⲓⲟⲛ ⲙⲏⲓϥ ⳿ⲉⲛⲉⲕⲃⲁⲗ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲙⲃⲟⲗ.
19 Gbogbo àwọn ti èmi bá fẹ́ ni èmi ń bá wí, tí mo sì ń nà: nítorí náà, ní ìtara, kì ìwọ sì ronúpìwàdà.
ⲓ̅ⲑ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲅⲁⲣ ⲛⲏ ⳿ⲉϣⲁⲓⲙⲉⲛⲣⲓⲧⲟⲩ ϣⲁⲓⲥⲁϩⲱⲟⲩ ϣⲁⲓϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲱⲟⲩ ⲭⲟϩ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲓⲙⲉⲧⲁⲛⲟⲓⲛ.
20 Kíyèsi i, èmi dúró ni ẹnu ìlẹ̀kùn, èmi sì ń kànkùn, bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ohun mi, tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn, èmi yóò sì wọlé tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bá a jẹun, àti òun pẹ̀lú mi.
ⲕ̅ϩⲏⲡⲡⲉ ⲅⲁⲣ ϯⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧ ϩⲓⲣⲉⲛ ⲡⲓⲣⲟ ⲟⲩⲟϩ ϯⲕⲱⲗϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲟⲩⲱⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲟ ⲛⲏⲓ ϯⲛⲁϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲁⲟⲩⲱⲙ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲛⲉⲙⲏⲓ.
21 Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi fún láti jókòó pẹ̀lú mi lórí ìtẹ́ mi, bí èmi pẹ̀lú ti ṣẹ́gun, tí mo sì jókòó pẹ̀lú Baba mi lórí ìtẹ́ rẹ̀.
ⲕ̅ⲁ̅ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲛⲁϭⲣⲟ ϯⲛⲁⲧⲏⲓⲥ ⲛⲁϥ ⲉⲑⲣⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ϩⲓ ⲡⲁⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲓϭⲣⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓϩⲉⲙⲥⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲁⲓⲱⲧ ϩⲓ ⲡⲉϥ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ.
22 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲛⲓⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ

< Revelation 3 >