< Revelation 22 +

1 Ó sì fi odò omi ìyè kan hàn mi, tí ó mọ́ bí kirisitali, tí ń tí ibi ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn jáde wá,
O anjo me mostrou o rio de água [que faz com que as pessoas que bebam da água ]vivam [para sempre. ]A água fluía faiscante e limpa como cristal [que faísca límpido. ]O rio brotava do trono onde [estão sentados ]Deus e [aquele que parece um ]cordeiro,
2 ní àárín ìgboro rẹ̀, àti níhà èkínní kejì odò náà, ni igi ìyè gbé wà, tí o máa ń so onírúurú èso méjìlá, a sì máa so èso rẹ̀ ni oṣooṣù ewé igi náà sí wà fún mímú àwọn orílẹ̀-èdè láradà.
O rio correu pelo meio da rua [principal ]da cidade. De cada lado do rio havia árvores [que produziam fruto que faz as pessoas ]viverem para sempre. [As árvores ]produzem doze [cargas ](OU[: tipos]) de frutos; [elas ]dão uma carga cada mês. [Os habitantes das ]nações [MTY] [utilizam ]as folhas das árvores para se fortalecerem/fortificarem.
3 Ègún kì yóò sì ṣí mọ: ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-àgùntàn ni yóò sì máa wà níbẹ̀; àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò sì máa sìn ín.
Nunca existirá [lá nada nem ninguém que Deus ]amaldiçoasse. Ficará na cidade o trono de Deus e [daquele que parece um ]cordeiro. [Consequentemente, ]os servos dele vão adorá-lo.
4 Wọ́n ó si máa rí ojú rẹ̀; orúkọ rẹ̀ yóò si máa wà ni iwájú orí wọn.
Eles olharão [diretamente ]para o rosto dele, e [Ele escreverá ]seu nome na testa deles.
5 Òru kì yóò sí mọ́; wọn kò sì ní wa ìmọ́lẹ̀ fìtílà, tàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn; nítorí pé Olúwa Ọlọ́run ni yóò tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn: wọn ó sì máa jẹ ọba láé àti láéláé. (aiōn g165)
Nunca mais haverá noite. [Os servos de Deus ]não precisarão da luz das lâmpadas nem da luz do sol, pois o Senhor Deus fará brilhar [sua ]luz sobre eles. Eles reinarão para sempre. (aiōn g165)
6 Ó sì wí fún mi pé, “Òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: Olúwa Ọlọ́run ẹ̀mí àwọn wòlíì ni ó sì ran angẹli rẹ̀ láti fi ohun tí ó ní láti ṣẹlẹ̀ láìpẹ́ yìí hàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.”
O anjo me disse: “Estas palavras [que Deus revelou a você ]são verdadeiras, e com certeza Ele vai cumpri-las. O Senhor Deus que [inspira ]os profetas, mandou seu anjo para mostrar àqueles que O servem os eventos que devem acontecer em breve”.
7 “Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán! Ìbùkún ni fún ẹni tí ń pa ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí mọ́!”
[Jesus diz a todo seu povo: ]“Escutem-me com cuidado! Volto logo; [Deus ]abençoará [abundantemente ]todos aqueles que obedecem à(s) mensagem/palavras que [foi/foram escrita/escritas ]neste livro”.
8 Èmi, Johanu, ni ẹni tí ó gbọ́ tí ó sì ri nǹkan wọ̀nyí. Nígbà tí mo sì gbọ́ tí mo sì rí, mo wólẹ̀ láti foríbalẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ angẹli náà, tí o fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi.
Sou eu, João, quem ouviu e viu [em uma visão ]estas coisas [que acabo de escrever.] Depois de ouvir e ver [estas coisas], logo me prostrei/ajoelhei aos pés do anjo que me mostrava estas coisas, para adorá-lo.
9 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Wó ò, má ṣe bẹ́ẹ̀, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ wòlíì, àti ti àwọn tí ń pa ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí mọ́. Foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run!”
Mas ele me disse: “Não [me adore, pois ]sou seu co-servo! Sou também co-servo dos seus irmãos crentes que são os profetas e co-servo daqueles que obedecem à mensagem deste livro. [Pelo contrário, ]adore a Deus!”
10 Ó sì wí fún mi pé, “Má ṣe fi èdìdì di ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí inú ìwé yìí, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
Ele também me disse: “Não lacre a mensagem daquilo que [Deus ]predisse neste livro, pois está quase na hora [MTY] de Ele [cumprir esta mensagem. ]
11 Ẹni tí ń ṣe aláìṣòótọ́, kí ó máa ṣe aláìṣòótọ́ nì só; àti ẹni tí ń ṣe ẹlẹ́gbin, kí ó máa ṣe ẹ̀gbin nì só; àti ẹni tí ń ṣe olódodo, kí ó máa ṣe òdodo nì só; àti ẹni tí ń ṣe mímọ́, kí ó máa ṣe mímọ́ nì só.”
[Ficando próxima aquela hora, se ]os que se comportam de forma iníqua [quiserem ]continuar a agir dessa maneira [IRO], [isso é lá com eles]! [Deus logo lhes retribuirá sua iniquidade. Se ]os iníquos [quiserem ]continuar assim [IRO], [que se virem! Deus logo lhes retribuirá sua maldade. ]Os que [se comportam ]de forma reta e justa devem continuar a agir de forma reta e justa. Os que são santos devem continuar a ser santos”.
12 “Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán; èrè mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, láti sán fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ yóò tí rí.
[Jesus diz a todas as pessoas: ]“Escutem! Volto logo! E retribuirei e galardoarei/recompensarei a todos os seres humanos de acordo com os feitos de cada um deles.
13 Èmi ni Alfa àti Omega, ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin.
[Sou ]eu que dou origem a todas as coisas [MET] e sou eu quem fará todas as coisas terminarem [MET]. Existo antes de [todas as coisas ]e existo no final [de todas as coisas ][DOU].
14 “Ìbùkún ni fún àwọn ti ń fọ aṣọ wọn, kí wọ́n lè ni ẹ̀tọ́ láti wá sí ibi igi ìyè náà, àti kí wọ́n lè gbà àwọn ẹnu ibodè wọ inú ìlú náà.
[Deus — abençoará abundantemente]/vai é contente com as pessoas que [lavam ]suas roupas[, limpando-se a si mesmas espiritualmente ][MET], porque elas poderão [comer do fruto ][MTY] da árvore [que capacita as pessoas a ]viverem [para sempre ]e porque [poderão ]entrar pelo portão da cidade [santa. ]
15 Nítorí ni òde ni àwọn ajá gbé wà, àti àwọn oṣó, àti àwọn àgbèrè, àti àwọn apànìyàn, àti àwọn abọ̀rìṣà, àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn èké tí ó sì ń hùwà èké.
Do lado de fora [ficam as pessoas imundas/malévolas, inclusive ]as que praticam idolatria, as que pecam sexualmente, as que assassinam [outras pessoas, ]as que adoram os ídolos e todas aquelas pessoas que gostam de mentir e mentem continuamente. [Tais pessoas nunca poderão entrar naquela cidade”.]
16 “Èmi, Jesu, ni ó rán angẹli mi láti jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí fún yin ní tí àwọn ìjọ. Èmi ni gbòǹgbò àti irú-ọmọ Dafidi, àti ìràwọ̀ òwúrọ̀ tí ń tàn.”
“Eu, Jesus, mandei meu anjo para dizer a vocês, membros das congregações, que [são verídicas todas ]estas coisas. Sou o descendente do [Rei ]Davi, [cuja vinda os profetas prometeram. ][MET]. Sou [aquele que é parecido ]com a brilhante estrela matutina [MET], aquele [que Moisés vaticinou”.]
17 Ẹ̀mí àti ìyàwó wí pé, “Máa bọ!” Àti ẹni tí ó ń gbọ́ kí ó wí pé, “Máa bọ̀!” Àti ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ kí ó wá, àti ẹni tí o bá sì fẹ́, kí ó gba omi ìyè náà lọ́fẹ̀ẹ́.
O Espírito [de Deus ]e [seu povo, que é parecido ][MET] com a noiva [de Cristo], dizem [a todos aqueles que desejam crer: ]“Venham!” Que todos os ouvintes [desta mensagem ]digam também [a todos aqueles que desejam crer]: “Venham!” Que os [sedentos venham, quais sejam ][MET], todos os que desejam a água [que capacita as pessoas ]a viverem [para sempre], que a recebam de graça!
18 Èmi kìlọ̀ fún olúkúlùkù ẹni tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí pé, bí ẹnikẹ́ni ba fi kún wọn, Ọlọ́run yóò fi kún àwọn ìyọnu tí a kọ sínú ìwé yìí fún un.
“Eu, [Jesus, ]advirto [solenemente ]a todos aqueles que ouvem as palavras relativas àquilo que já predisse neste livro, [assim: ]Se alguém acrescentar qualquer coisa a estas palavras, Deus vai fazê-lo sofrer as pragas que são descritas {que descrevi} neste livro.
19 Bí ẹnikẹ́ni bá sì mú kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìwé ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, Ọlọ́run yóò sì mú ipa tirẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, àti kúrò nínú ìlú mímọ́ náà, àti kúrò nínú àwọn ohun tí a kọ sínú ìwé yìí.
Se alguém cortar quaisquer palavras sobre aquilo que profetizei neste livro, Deus tirará o direito dele [de comer do fruto ][MTY] da árvore [que capacita as pessoas a ]viverem [para sempre. ]Ele [também vai tirar-lhe ]o direito [de entrar ]na cidade de Deus. [Ambas as coisas ]são descritas {descrevi} neste livro”.
20 Ẹni tí ó jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí wí pé, “Nítòótọ́ èmi ń bọ̀ kánkán.” Àmín. Máa bọ̀, Jesu Olúwa!
[Jesus, ]que afirma serem verídicas [todas ]estas coisas, diz: “Com certeza venho/volto em breve!” [Eu, João, respondo: ]“Assim seja! Senhor Jesus, venha já!”
21 Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àmín.
[Peço em oração que nosso ]Senhor Jesus [continue ]abençoando/agindo bondosamente para com todos [vocês, o povo de Deus]. Assim seja!

< Revelation 22 +