< Revelation 22 +

1 Ó sì fi odò omi ìyè kan hàn mi, tí ó mọ́ bí kirisitali, tí ń tí ibi ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn jáde wá,
Han viste meg en elv med livets vann, glitrende som krystall. Den kom fra Guds og Lammets trone.
2 ní àárín ìgboro rẹ̀, àti níhà èkínní kejì odò náà, ni igi ìyè gbé wà, tí o máa ń so onírúurú èso méjìlá, a sì máa so èso rẹ̀ ni oṣooṣù ewé igi náà sí wà fún mímú àwọn orílẹ̀-èdè láradà.
Midt i den store gaten fløt den fram. På begge sider av elven vokste livets tre, som bærer frukt tolv ganger om året og gir avling hver måned. Bladene fra trærne er medisin for alle folk.
3 Ègún kì yóò sì ṣí mọ: ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-àgùntàn ni yóò sì máa wà níbẹ̀; àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò sì máa sìn ín.
Ingen som Gud har dømt til å gå under, eksisterer lenger. Guds og Lammets trone skal stå i byen, og tjenerne hans vil tilbe ham.
4 Wọ́n ó si máa rí ojú rẹ̀; orúkọ rẹ̀ yóò si máa wà ni iwájú orí wọn.
De skal se ham ansikt til ansikt, og navnet hans vil stå skrevet på pannene deres.
5 Òru kì yóò sí mọ́; wọn kò sì ní wa ìmọ́lẹ̀ fìtílà, tàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn; nítorí pé Olúwa Ọlọ́run ni yóò tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn: wọn ó sì máa jẹ ọba láé àti láéláé. (aiōn g165)
Det skal aldri mer bli mørkt, og ingen skal lenger behøve lampe eller solens lys, for Herren Gud skal lyse over alle. De skal regjere i all evighet. (aiōn g165)
6 Ó sì wí fún mi pé, “Òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: Olúwa Ọlọ́run ẹ̀mí àwọn wòlíì ni ó sì ran angẹli rẹ̀ láti fi ohun tí ó ní láti ṣẹlẹ̀ láìpẹ́ yìí hàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.”
Etter dette sa engelen til meg:”Mitt budskap er troverdig og sant. Herren Gud, som gir budskapet til profetene, han har sendt sin engel for å vise tjenerne sine det som snart vil skje.”
7 “Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán! Ìbùkún ni fún ẹni tí ń pa ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí mọ́!”
”Se”, sier Jesus,”jeg kommer snart! Lykkelig er den som tar være på budskapet fra Gud som er skrevet ned i denne boken.”
8 Èmi, Johanu, ni ẹni tí ó gbọ́ tí ó sì ri nǹkan wọ̀nyí. Nígbà tí mo sì gbọ́ tí mo sì rí, mo wólẹ̀ láti foríbalẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ angẹli náà, tí o fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi.
Det var jeg, Johannes, som fikk høre og se alt dette. Da jeg hadde hørt og sett alt, falt jeg ned for å hylle engelen som hadde vist det for meg.
9 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Wó ò, má ṣe bẹ́ẹ̀, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ wòlíì, àti ti àwọn tí ń pa ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí mọ́. Foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run!”
Han sa:”Nei, gjør ikke det! Jeg er bare Guds tjener, akkurat som du og de andre profetene som bar fram Guds budskap på samme måten som alle dem som tar være på det som står i denne boken. Det er Gud du skal tilbe.”
10 Ó sì wí fún mi pé, “Má ṣe fi èdìdì di ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí inú ìwé yìí, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
Han sa til meg:”Ikke hold budskapet fra Gud hemmelig, det som du har skrevet ned i denne boken. Det drøyer ikke lenge før alt dette går i oppfyllelse.
11 Ẹni tí ń ṣe aláìṣòótọ́, kí ó máa ṣe aláìṣòótọ́ nì só; àti ẹni tí ń ṣe ẹlẹ́gbin, kí ó máa ṣe ẹ̀gbin nì só; àti ẹni tí ń ṣe olódodo, kí ó máa ṣe òdodo nì só; àti ẹni tí ń ṣe mímọ́, kí ó máa ṣe mímọ́ nì só.”
En kort periode til får den onde fortsette å være ond, og den som synder, får fortsette å synde litt til. Den som er god, fortsetter å være god, og den som lever fullt og helt for Gud, fortsetter å leve fullt og helt for Gud.”
12 “Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán; èrè mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, láti sán fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ yóò tí rí.
”Se”, sier Jesus,”jeg kommer snart. Jeg har med meg lønnen som skal bli delt ut til hver og en etter gjerningene hans.
13 Èmi ni Alfa àti Omega, ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin.
Jeg er alfa og omega, den første og den siste, begynnelsen og slutten på alle ting.”
14 “Ìbùkún ni fún àwọn ti ń fọ aṣọ wọn, kí wọ́n lè ni ẹ̀tọ́ láti wá sí ibi igi ìyè náà, àti kí wọ́n lè gbà àwọn ẹnu ibodè wọ inú ìlú náà.
Lykkelige er de som vasker klærne sine rene. De skal få rett til å spise av frukten fra livets tre og gå inn gjennom portene i byen.
15 Nítorí ni òde ni àwọn ajá gbé wà, àti àwọn oṣó, àti àwọn àgbèrè, àti àwọn apànìyàn, àti àwọn abọ̀rìṣà, àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn èké tí ó sì ń hùwà èké.
Utenfor står de som har vendt Gud ryggen, de som har drevet med magi og okkultisme, de som har hengitt seg til seksuell løssluppenhet, morderne, avgudsdyrkerne og alle som har elsket løgnen og levd livet sitt i falskhet.
16 “Èmi, Jesu, ni ó rán angẹli mi láti jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí fún yin ní tí àwọn ìjọ. Èmi ni gbòǹgbò àti irú-ọmọ Dafidi, àti ìràwọ̀ òwúrọ̀ tí ń tàn.”
”Jeg, Jesus, har sendt min engel til dere for å fortelle om dette til menighetene. Jeg er etterkommer av kong David og arving til hans trone. Jeg er den strålende morgenstjernen.”
17 Ẹ̀mí àti ìyàwó wí pé, “Máa bọ!” Àti ẹni tí ó ń gbọ́ kí ó wí pé, “Máa bọ̀!” Àti ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ kí ó wá, àti ẹni tí o bá sì fẹ́, kí ó gba omi ìyè náà lọ́fẹ̀ẹ́.
Guds Ånd og bruden sier:”Kom!” Når du hører dette, skal du svare:”Kom!” Du som er tørst, kom, for den som vil, kan få drikke av livets vann helt gratis.
18 Èmi kìlọ̀ fún olúkúlùkù ẹni tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí pé, bí ẹnikẹ́ni ba fi kún wọn, Ọlọ́run yóò fi kún àwọn ìyọnu tí a kọ sínú ìwé yìí fún un.
Jeg advarer alle som hører budskapet fra Gud i denne boken: Dersom noen legger til noe i det som er skrevet, da skal Gud la ham bli rammet av alle de plagene som det står om i boken.
19 Bí ẹnikẹ́ni bá sì mú kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìwé ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, Ọlọ́run yóò sì mú ipa tirẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, àti kúrò nínú ìlú mímọ́ náà, àti kúrò nínú àwọn ohun tí a kọ sínú ìwé yìí.
Dersom noen tar bort noe fra det budskapet Gud har båret fram, da skal Gud ta bort hans del i livets tre og den Hellige byen, som det står om i denne boken.
20 Ẹni tí ó jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí wí pé, “Nítòótọ́ èmi ń bọ̀ kánkán.” Àmín. Máa bọ̀, Jesu Olúwa!
Han som forteller dette, sier:”Ja, jeg kommer snart!” Ja, det er sant! Kom, Herre Jesus!
21 Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àmín.
Ta imot ønsket om at Herren Jesu godhet og kjærlighet må være med dere alle.

< Revelation 22 +