< Revelation 2 >
1 “Sí angẹli ìjọ ní Efesu kọ̀wé: Nǹkan wọ̀nyí ní ẹni tí ó mú ìràwọ̀ méje náà ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ wí, ẹni tí ń rìn ní àárín ọ̀pá wúrà fìtílà méje.
"To the minister of the Church in Ephesus write as follows: "'This is what He who holds the seven stars in the grasp of His right hand says--He who walks to and fro among the seven lampstands of gold.
2 Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti làálàá rẹ, àti ìfaradà rẹ, àti bí ara rẹ kò ti gba àwọn ẹni búburú, àti bí ìwọ sì ti dán àwọn tí ń pe ara wọn ní aposteli, tí wọ́n kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ wo, tí ìwọ sì rí pé èké ni wọ́n,
I know your doings and your toil and patient suffering. And I know that you cannot tolerate wicked men, but have put to the test those who say that they themselves are Apostles but are not, and you have found them to be liars.
3 tí ìwọ sì faradà ìyà, àti nítorí orúkọ mi tí ó sì rọ́jú, tí àárẹ̀ kò sì mú ọ.
And you endure patiently and have borne burdens for My sake and have never grown weary.
4 Síbẹ̀ èyí ni mo rí wí sí ọ, pé, ìwọ ti fi ìfẹ́ ìṣáájú rẹ sílẹ̀.
Yet I have this against you--that you no longer love Me as you did at first.
5 Rántí ibi tí ìwọ ti gbé ṣubú! Ronúpìwàdà, kí ó sì ṣe iṣẹ́ ìṣáájú; bí kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó sì tọ̀ ọ́ wá, èmi ó sì ṣí ọ̀pá fìtílà rẹ̀ kúrò ní ipò rẹ̀, bí kò ṣe bí ìwọ bá ronúpìwàdà.
Be mindful, therefore, of the height from which you have fallen. Repent at once, and act as you did at first, or else I will surely come and remove your lampstand out of its place--unless you repent.
6 Ṣùgbọ́n èyí ni ìwọ ní, pé ìwọ kórìíra ìṣe àwọn Nikolatani, èyí tí èmi pẹ̀lú sì kórìíra.
Yet this you have in your favor: you hate the doings of the Nicolaitans, which I also hate.
7 Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi èso igi ìyè nì fún jẹ, tí ń bẹ láàrín Paradise Ọlọ́run.
"'Let all who have ears give heed to what the Spirit is saying to the Churches. To him who overcomes I will give the privilege of eating the fruit of the Tree of Life, which is in the Paradise of God.'
8 “Àti sí angẹli ìjọ ní Smirna kọ̀wé. Nǹkan wọ̀nyí ni ẹni tí í ṣe ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn wí, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè.
"To the minister of the Church at Smyrna write as follows: "'This is what the First and the Last says--He who died and has returned to life.
9 Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti ìpọ́njú, àti àìní rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́, èmi sì mọ ọ̀rọ̀-òdì tí àwọn tí ń wí pé, Júù ni àwọn tìkára wọn, tí wọn kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ Sinagọgu ti Satani.
Your sufferings I know, and your poverty--but you are rich--and the evil name given you by those who say that they themselves are Jews, and are not, but are Satan's synagogue.
10 Má ṣe bẹ̀rù ohunkóhun tí ìwọ ń bọ wá jìyà rẹ̀. Kíyèsi i, èṣù yóò gbé nínú yín jù sínú túbú, kí a lè dán yin wò; ẹ̀yin ó sì ní ìpọ́njú ní ọjọ́ mẹ́wàá, ìwọ ṣa ṣe olóòtítọ́ dé ojú ikú, èmi ó sì fi adé ìyè fún ọ.
Dismiss your fears concerning all that you are about to suffer. I tell you that the Devil is about to throw some of you into prison that you may be put to the test, and for ten days you will have to endure persecution. Be faithful to the End, even if you have to die, and then I will give you the victor's Wreath of Life.
11 Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun kì yóò fi ara pa nínú ikú kejì.
"'Let all who have ears give heed to what the Spirit is saying to the Churches. He who overcomes shall be in no way hurt by the Second Death.'
12 “Àti sì angẹli ìjọ ni Pargamu kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ní idà mímú olójú méjì.
"To the minister of the Church at Pergamum write as follows: "'This is what He who has the sharp, two-edged sword says. I know where you dwell.
13 Èmí mọ̀ ibi tí ìwọ ń gbé, àní ibi tí ìtẹ́ Satani wà. Síbẹ̀ ìwọ di orúkọ mi mú ṣinṣin. Ìwọ kò sì sẹ́ ìgbàgbọ́ nínú mi, pàápàá jùlọ ni ọjọ́ Antipa ẹlẹ́rìí mi, olóòtítọ́ ènìyàn, ẹni tí wọn pa láàrín yín, níbi tí Satani ń gbé.
Satan's throne is there; and yet you are true to Me, and did not deny your faith in Me, even in the days of Antipas My witness and faithful friend, who was put to death among you, in the place where Satan dwells.
14 Ṣùgbọ́n mo ni nǹkan díẹ̀ wí sí ọ; nítorí tí ìwọ ní àwọn kan tí ó di ẹ̀kọ́ Balaamu mú síbẹ̀, ẹni tí ó kọ́ Balaki láti mú ohun ìkọ̀sẹ̀ wá síwájú àwọn ọmọ Israẹli, láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sí òrìṣà, àti láti máa ṣe àgbèrè.
Yet I have a few things against you, because you have with you some that cling to the teaching of Balaam, who taught Balak to put a stumbling-block in the way of the descendants of Israel--to eat what had been sacrificed to idols, and commit fornication.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ní àwọn tí ó gbá ẹ̀kọ́ àwọn Nikolatani pẹ̀lú, ohun tí mo kórìíra.
So even you have some that cling in the same way to the teaching of the Nicolaitans.
16 Nítorí náà, ronúpìwàdà; bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó tọ̀ ọ́ wá nísinsin yìí, èmí o sì fi idà ẹnu mi bá wọn jà.
Repent, at once; or else I will come to you quickly, and will make war upon them with the sword which is in My mouth.
17 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí o bá ṣẹ́gun ni èmi o fi manna tí ó pamọ́ fún, èmi ó sì fún un ni òkúta funfun kan, àti sára òkúta náà ni a kọ orúkọ tuntun kan, tí ẹnìkan kò mọ̀ bí kò ṣe ẹni tí ó gbà á.
"'Let all who have ears give heed to what the Spirit is saying to the Churches. He who overcomes--to him I will give some of the hidden Manna, and a white stone; and--written upon the stone and known only to him who receives it-- a new name.'
18 “Àti sí angẹli ìjọ ní Tiatira kọ̀wé. Nǹkan wọ̀nyí ni Ọmọ Ọlọ́run wí, ẹni tí ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, tí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára.
"To the minister of the Church at Thyateira write as follows: "'This is what the Son of God says--He who has eyes like a flame of fire, and feet resembling silver-bronze.
19 Èmi mọ̀ iṣẹ́, ìfẹ́, àti ìgbàgbọ́ àti ìsìn àti sùúrù rẹ̀; àti pé iṣẹ́ rẹ̀ ìkẹyìn ju tí ìṣáájú lọ.
I know your doings, your love, your faith, your service, and your patient endurance; and that of late you have toiled harder than you did at first.
20 Ṣùgbọ́n èyí ni mo rí wí sí ọ, nítorí tí ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún obìnrin Jesebeli tí ó ń pe ara rẹ̀ ní wòlíì. Nípasẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó sì ń kọ́ àwọn ìránṣẹ́ mi, ó sì ń tàn wọ́n láti máa ṣe àgbèrè, àti láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sì òrìṣà.
Yet I have this against you, that you tolerate the woman Jezebel, who calls herself a prophetess and by her teaching leads astray My servants, so that they commit fornication and eat what has been sacrificed to idols.
21 Èmi fi àkókò fún un, láti ronúpìwàdà; ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ ronúpìwàdà àgbèrè rẹ̀.
I have given her time to repent, but she is determined not to repent of her fornication.
22 Nítorí náà, èmi ó gbé e sọ sí orí àkéte ìpọ́njú, àti àwọn tí ń bá a ṣe panṣágà ni èmi ó fi sínú ìpọ́njú ńlá, bí kò ṣe bí wọ́n bá ronúpìwàdà iṣẹ́ wọn.
I tell you that I am about to cast her upon a bed of sickness, and I will severely afflict those who commit adultery with her, unless they repent of conduct such as hers.
23 Èmi o pa àwọn ọmọ rẹ̀ run; gbogbo ìjọ ni yóò sì mọ̀ pé, èmi ni ẹni tí ń wádìí inú àti ọkàn, èmi ó sì fi fún olúkúlùkù yín gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
Her children too shall surely die; and all the Churches shall come to know that I am He who searches into men's inmost thoughts; and to each of you I will give a requital which shall be in accordance with what your conduct has been.
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni mò ń sọ fún, ẹ̀yin ìyókù tí ń bẹ ní Tiatira, gbogbo ẹ̀yin tí kò ni ẹ̀kọ́ yìí, ti kò ì tí ì mọ̀ ohun tí wọn pè ni ohun ìjìnlẹ̀ Satani, èmi kò di ẹrù mìíràn rù yín,
But to you, the rest of you in Thyateira, all who do not hold this teaching and are not the people who have learnt the "deep things," as they call them (the deep things of Satan!) --to you I say that I lay no other burden on you.
25 ṣùgbọ́n èyí tí ẹ̀yin ní, ẹ di mú ṣinṣin títí èmi ó fi dé.
Only that which you already possess, cling to until I come.
26 Ẹni tí ó bá sì ṣẹ́gun, àti tí ó sì ṣe ìfẹ́ mi títí dé òpin, èmi ó fún un láṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè:
"'And to him who overcomes and obeys My commands to the very end, I will give authority over the nations of the earth.
27 ‘Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn; gẹ́gẹ́ bí a ti ń fọ́ ohun èlò amọ̀kòkò ni a ó fọ́ wọn túútúú,’ gẹ́gẹ́ bí èmi pẹ̀lú tí gbà àṣẹ láti ọ̀dọ̀ Baba mi.
And he shall be their shepherd, ruling them with a rod of iron, just as earthenware jars are broken to pieces; and his power over them shall be like that which I Myself have received from My Father;
28 Èmi yóò sì fi ìràwọ̀ òwúrọ̀ fún un.
and I will give him the Morning Star.
29 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
Let all who have ears give heed to what the Spirit is saying to the Churches.'