< Revelation 19 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo gbọ́ ohùn ńlá ní ọ̀run bí ẹni pé tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, ń wí pé: “Haleluya! Ti Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà, àti ọlá àti agbára,
After this I seemed to hear the far-echoing voices of a great multitude in Heaven, who said, "Hallelujah! The salvation and the glory and the power belong to our God.
2 nítorí òtítọ́ àti òdodo ni ìdájọ́ rẹ̀. Nítorí o ti ṣe ìdájọ́ àgbèrè ńlá a nì, tí o fi àgbèrè rẹ̀ ba ilẹ̀ ayé jẹ́, ó sì ti gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀ náà.”
True and just are His judgments, because He has judged the great Harlot who was corrupting the whole earth with her fornication, and He has taken vengeance for the blood of His bondservants which her hands have shed."
3 Àti lẹ́ẹ̀kejì wọ́n wí pé: “Haleluya! Èéfín rẹ̀ sì gòkè lọ láé àti láéláé.” (aiōn )
And a second time they said, "Hallelujah! For her smoke ascends until the Ages of the Ages." (aiōn )
4 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún nì, àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin nì sì wólẹ̀, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run tí ó jókòó lórí ìtẹ́, wí pé: “Àmín, Haleluya!”
And the twenty-four Elders and the four living creatures fell down and worshipped God who sits upon the throne. "Even so," they said; "Hallelujah!"
5 Ohùn kan sì ti ibi ìtẹ́ náà jáde wá, wí pé: “Ẹ máa yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti èwe àti àgbà!”
And from the throne there came a voice which said, "Praise our God, all you His bondservants--you who fear Him, both the small and the great."
6 Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àti bí ìró omi púpọ̀, àti bí ìró àrá ńlá ńlá, ń wí pé: “Haleluya! Nítorí Olúwa Ọlọ́run wa, Olódùmarè ń jẹ ọba.
And I seemed to hear the voices of a great multitude and the sound of many waters and of loud peals of thunder, which said, "Hallelujah! Because the Lord our God, the Ruler of all, has become King.
7 Ẹ jẹ́ kí a yọ̀, kí inú wa kí ó sì dùn gidigidi, kí a sì fi ògo fún un. Nítorí pé ìgbéyàwó Ọ̀dọ́-Àgùntàn dé, aya rẹ̀ sì ti múra tán.
Let us rejoice and triumph and give Him the glory; for the time for the marriage of the Lamb has come, and His Bride has made herself ready."
8 Òun ni a sì fi fún pé kí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́ tí ó funfun gbòò.” (Nítorí pé aṣọ ọ̀gbọ̀ nì dúró fún iṣẹ́ òdodo àwọn ènìyàn mímọ́.)
And she was permitted to array herself in fine linen, shining and spotless; the fine linen being the righteous actions of God's people.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, ‘Ìbùkún ni fún àwọn tí a pè sí àsè alẹ́ ìgbéyàwó ọ̀dọ́-àgùntàn.’” Ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ òtítọ́ Ọlọ́run.”
And he said to me, "Write as follows: 'Blessed are those who receive an invitation to the Marriage Supper of the Lamb.'" And he added, still addressing me, "These are truly the words of God."
10 Mo sì wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ láti foríbalẹ̀ fún un. Ó sì wí fún mi pé, “Wò ó, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ tí wọ́n di ẹ̀rí Jesu mú. Foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run: nítorí pé ẹ̀rí Jesu ni ìsọtẹ́lẹ̀.”
Then I fell at his feet to worship him. But he exclaimed, "Oh, do not do that. I am a fellow bondservant of yours and a fellow bondservant of your brethren who have borne testimony to Jesus. Worship God." Testimony to Jesus is the spirit which underlies Prophecy.
11 Mo sì rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, sì wò ó, ẹṣin funfun kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni à ń pè ní Olódodo àti Olóòtítọ́, nínú òdodo ni ó sì ń ṣe ìdájọ́, tí ó ń jagun.
Then I saw a door open in Heaven, and a white horse appeared. Its rider was named "Faithful and True" --being One who in righteousness acts as Judge, and makes war.
12 Ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, àti ní orí rẹ̀ ni adé púpọ̀ wà; ó sì ní orúkọ kan tí a kọ, tí ẹnikẹ́ni kò mọ́, bí kò ṣe òun tìkára rẹ̀.
His eyes were like a flame of fire, and on His head were many kingly crowns; and He has a name written upon Him which no one but He Himself knows.
13 A sì wọ̀ ọ́ ní aṣọ tí a tẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀, a sì ń pe orúkọ rẹ̀ ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
The outer garment in which He is clad has been dipped in blood and His name is THE WORD OF GOD.
14 Àwọn ogun tí ń bẹ ní ọ̀run tí a wọ̀ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́, funfun àti mímọ́, sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn lórí ẹṣin funfun.
The armies in Heaven followed Him--mounted on white horses and clothed in fine linen, white and spotless.
15 Àti láti ẹnu rẹ̀ ni idà mímú ti ń jáde lọ, kí ó lè máa fi sá àwọn orílẹ̀-èdè: “Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn.” Ó sì ń tẹ ìfúntí àti ìbínú Ọlọ́run Olódùmarè.
From His mouth there comes a sharp sword with which He will smite the nations; and He will Himself be their Shepherd, ruling them with a scepter of iron; and it is His work to tread the winepress of the fierce anger of God, the Ruler of all.
16 Ó sì ní lára aṣọ rẹ̀ àti ni ìtàn rẹ̀ orúkọ kan tí a kọ: Ọba àwọn ọba àti Olúwa àwọn olúwa.
And on His outer garment and on His thigh He has a name written, KING OF KINGS AND LORD OF LORDS.
17 Mo sì rí angẹli kan dúró nínú oòrùn; ó sì fi ohùn rara kígbe, ó ń wí fún gbogbo àwọn ẹyẹ tí ń fò ní agbede-méjì ọ̀run pé, “Ẹ wá ẹ sì kó ara yín jọ pọ̀ sí àsè ńlá Ọlọ́run;
And I saw a single angel standing in the full light of the sun, who cried in a loud voice to all the birds that flew across the sky, "Come and be present at God's great supper,
18 kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ ẹran-ara àwọn ọba, àti ẹran-ara àwọn olórí ogun àti ẹran-ara àwọn ènìyàn alágbára, àti ẹran àwọn ẹṣin, àti ti àwọn tí ó jókòó lórí wọn, àti ẹran-ara ènìyàn gbogbo, àti ti òmìnira, àti ti ẹrú, àti ti èwe àti ti àgbà.”
that you may feast on the flesh of kings and the flesh of generals and the flesh of mighty men, on the flesh of horses and their riders, and on the flesh of all mankind, whether they are free men or slaves, great men or small."
19 Mo sì rí ẹranko náà àti àwọn ọba ayé, àti àwọn ogun wọn tí a gbá jọ láti bá ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà àti ogun rẹ̀ jagun.
And I saw the Wild Beast, and the kings of the earth, and their armies, all assembled to make war, once for all, against the Rider upon the horse and against His army. And the Wild Beast was captured, and with him the false Prophet
20 A sì mú ẹranko náà, àti wòlíì èké nì pẹ̀lú rẹ̀, tí ó ti ń ṣe iṣẹ́ ìyanu níwájú rẹ̀, èyí tí ó fi ń tan àwọn tí ó gba àmì ẹranko náà àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún àwòrán rẹ̀ jẹ. Àwọn méjèèjì yìí ni a sọ láààyè sínú adágún iná tí ń fi sulfuru jó. (Limnē Pyr )
who had done the miracles in his presence with which he had led astray those who had received the mark of the Wild Beast, and those who worshipped his statue. Both of them were thrown alive into the Lake of fire that was all ablaze with sulphur. (Limnē Pyr )
21 Àwọn ìyókù ni a sì fi idà ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà pa, àní idà tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde, gbogbo àwọn ẹyẹ sì ti ipa ẹran-ara wọn yó.
But the rest were killed with the sword that came from the mouth of the Rider on the horse. And the birds all fed ravenously upon their flesh.