< Revelation 18 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo sì rí angẹli mìíràn, ó ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá ti òun ti agbára ńlá; ilẹ̀ ayé sì ti ipa ògo rẹ̀ mọ́lẹ̀.
A potemem widział drugiego Anioła zstępującego z nieba, mającego moc wielką i oświeciła się ziemia od chwały jego.
2 Ó sì kígbe ní ohùn rara, wí pé: “Babeli ńlá ṣubú! Ó ṣubú! Ó sì di ibùjókòó àwọn ẹ̀mí èṣù, àti ihò fún ẹ̀mí àìmọ́ gbogbo, àti ilé fún ẹyẹ àìmọ́ gbogbo, ilé fún ẹranko ìríra àti àìmọ́ gbogbo.
I zawołał potężnie głosem wielkim, mówiąc: Upadł, upadł Babilon on wielki i stał się przybytkiem czartów i mieszkaniem wszelkiego ducha nieczystego, i mieszkaniem wszelkiego ptastwa nieczystego i przemierzłego.
3 Nítorí nípa ọtí wáìnì ìrunú àgbèrè rẹ̀ ni gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú. Àwọn ọba ayé sì ti bá a ṣe àgbèrè, àti àwọn oníṣòwò ayé sì di ọlọ́rọ̀ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọ̀bìà rẹ̀.”
Iż z win zapalczywości wszeteczeństwa jego piły wszystkie narody, a królowie ziemi wszeteczeństwo z nim płodzili, i kupcy ziemscy z zbytecznej rozkoszy jego zbogacieli.
4 Mo sì gbọ́ ohùn mìíràn láti ọ̀run wá, wí pé: “‘Ẹ ti inú rẹ̀ jáde, ẹ̀yin ènìyàn mi,’ kí ẹ ma bá a ṣe alábápín nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, kí ẹ ma bà á sì ṣe gbà nínú ìyọnu rẹ̀.
I słyszałem inszy głos z nieba mówiący: Wynijdźcie z niego, ludu mój! abyście nie byli uczestnikami grzechów jego, a iżbyście nie wzięli z plag jego.
5 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ga títí dé ọ̀run, Ọlọ́run sì ti rántí àìṣedéédéé rẹ̀.
Albowiem dosięgły grzechy jego aż do nieba i wspomniał Bóg na nieprawości jego.
6 San an fún un, àní bí òun tí san án fún ní, kí ó sì ṣe e ni ìlọ́po méjì fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀, nínú ago náà tí o ti kún, òun ni kí ẹ sì kún fún un ni méjì.
Oddajcież mu, jako i on oddawał wam, a w dwójnasób oddajcie mu według uczynków jego; w kubku, który wam nalewał, nalejcie mu w dwójnasób.
7 Níwọ́n bí o ti yin ara rẹ̀ lógo tó, tí ó sì hùwà wọ̀bìà, níwọ̀n bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ dá a lóró kí ẹ sì fún un ní ìbànújẹ́; nítorí tí ó wí ní ọkàn rẹ̀ pé, ‘Mo jókòó bí ọbabìnrin, èmi kì sì í ṣe opó, èmí kì yóò sì rí ìbànújẹ́ láé.’
Jako się wiele chlubił i rozkoszował, tak mu wiele dajcie mąk i smutku; bo mówi w sercu swojem: Siedzę jako królowa, a nie jestem wdową, i smutku nie ujrzę.
8 Nítorí náà, ní ọjọ́ kan ni ìyọnu rẹ̀ yóò dé, ikú, àti ìbìnújẹ́, àti ìyàn; a ó sì fi iná sun ún pátápátá: nítorí pé alágbára ni Olúwa Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Przetoż w jeden dzień przyjdą plagi jego, śmierć i smutek, i głód, i ogniem będzie spalony; bo mocny jest Pan Bóg, który go osądzi.
9 “Àti àwọn ọba ayé, tí ó ti ń bá a ṣe àgbèrè, tiwọn sì ń hùwà wọ̀bìà, yóò sì pohùnréré ẹkún lé e lórí, nígbà tí wọn bá wo èéfín ìjóná rẹ̀.
I będą go płakać, i narzekać nad nim będą królowie ziemi, którzy z nim wszeteczeństwo płodzili i rozkoszowali, gdy ujrzą dym zapalenia jego.
10 Wọ́n ó dúró ní òkèrè réré nítorí ìbẹ̀rù iṣẹ́ oró rẹ̀, wọn ó máa wí pé: “‘Ègbé! Ègbé, ni fún ìlú ńlá náà, Babeli ìlú alágbára nì! Nítorí ní wákàtí kan ni ìdájọ́ rẹ dé!’
Z daleka stojąc dla bojaźni męki jego i mówiąc: Biada, biada, miasto ono wielkie Babilon, miasto ono mocne, iż w jednę godzinę przyszedł sąd twój!
11 “Àwọn oníṣòwò ayé sì ń sọkún, wọn sì ń ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, nítorí pé ẹnikẹ́ni kò rà ọjà wọn mọ́.
Do tego i kupcy ziemscy płakać będą i narzekać nad niem, przeto iż towaru ich żaden więcej kupować nie będzie,
12 Ọjà wúrà, àti ti fàdákà, àti ti òkúta iyebíye, àti ti perli, àti ti aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́, àti tí elése àlùkò, àti ti ṣẹ́dà, àti ti òdòdó, àti ti gbogbo igi olóòórùn dídùn, àti ti olúkúlùkù ohun èlò tí a fi igi iyebíye ṣe, àti ti idẹ, àti ti irin, àti ti òkúta mabu.
Towaru złota i srebra, i kamienia drogiego, i pereł, i lnu cienkiego, i purpury, i jedwabiu, i szarłatu, i wszelkiego drzewa tyinowego, i wszelkiego naczynia słoniowego, i wszelkiego naczynia z drzewa najkosztowniejszego, i z miedzi, i z żelaza, i z marmuru,
13 Àti ti Kinamoni, àti ti onírúurú ohun olóòórùn dídùn, àti ti ohun ìkunra, àti tí tùràrí, àti ti ọtí wáìnì, àti ti òróró, àti ti ìyẹ̀fun dáradára, àti ti alikama, àti ti ẹran ńlá, àti ti àgùntàn, àti ti ẹṣin, àti ti kẹ̀kẹ́, àti ti ẹrú, àti ti ọkàn ènìyàn.
I cynamonu, i kadzenia, i maści, i kadzidła, i wina, i oliwy, i mąki czystej, i pszenicy, i bydła, i owiec, i koni, i wozów, i niewolników, i dusz ludzkich.
14 “Àti àwọn èso tí ọkàn rẹ̀ ń ṣe. Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí, si lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, àti ohun gbogbo tí ó dùn tí ó sì dára ṣègbé mọ́ ọ lójú, kì yóò sì tún rí wọn mọ́ láé.
I owoce pożądliwości duszy twojej odeszły od ciebie, i wszystkie rzeczy tłuste i świetne odeszły od ciebie, a tych rzeczy już więcej nie znajdziesz.
15 Àwọn oníṣòwò nǹkan wọ̀nyí, tí a ti ipa rẹ̀ sọ di ọlọ́rọ̀, yóò dúró ní òkèrè réré nítorí ìbẹ̀rù iṣẹ́ oró rẹ̀, wọn o máa sọkún, wọ́n ó sì máa ṣọ̀fọ̀,
Kupcy tych rzeczy, zbogaciwszy się tem, z daleka stać będą dla bojaźni męki jego, płacząc i narzekając,
16 wí pé: “‘Ègbé! Ègbé, ni fún ìlú ńlá nì, tí a wọ̀ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́, àti ti elése àlùkò, àti ti òdòdó, àti ti a sì fi wúrà ṣe ní ọ̀ṣọ́, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti peali!
A mówiąc: Biada, biada, miasto ono wielkie, które było obleczone w bisior, i w purpurę, i w szarłat, i uzłocone złotem, i kamieniem drogim, i perłami; gdyż w jednej godzinie zginęło tak wielkie bogactwo.
17 Nítorí pé ní wákàtí kan ni ọrọ̀ ti o pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ di asán!’ “Àti olúkúlùkù ẹni tí ń rin ojú omi lọ sí ibikíbi, àti àwọn ti ń ṣiṣẹ́ nínú ọkọ àwọn ti ń ṣòwò ojú Òkun dúró ní òkèrè réré,
I wszelki sternik, i wszystko mnóstwo ludu, które jest na okręcie, i żeglarze, i którzykolwiek na morzu pożytku szukają, z daleka stanęli.
18 wọ́n sì kígbe nígbà tí wọ́n rí èéfín jíjóná rẹ́, wí pé, ‘Ìlú wo ni o dàbí ìlú yìí?’
I zawołali, widząc dym zapalenia jego, mówiąc: Któreż miasto było podobne temu miastu wielkiemu?
19 Wọ́n sì kú ekuru sí orí wọn, wọ́n kígbe, wọ́n sọkún, wọn sì ń ṣọ̀fọ̀, wí pé: “‘Ègbé! Ègbé, ni fún ìlú ńlá náà, nínú èyí tí a sọ gbogbo àwọn tí ó ni ọkọ̀ ní Òkun di ọlọ́rọ̀ nípa ohun iyebíye rẹ̀! Nítorí pé ni wákàtí kan, a sọ ọ́ di ahoro.’
A sypali proch na głowy swoje i wołali, płacząc i smucąc się, i mówiąc: Biada, biada, miasto ono wielkie, w którem zbogatnieli wszyscy, którzy mieli okręty na morzu z dostatków jego, iż jednej godziny spustoszało!
20 “Yọ̀ lórí rẹ̀, ìwọ ọ̀run! Ẹ yọ̀, ẹ̀yin ènìyàn Ọlọ́run! Ẹ yọ̀, ẹ̀yin aposteli mímọ́ àti wòlíì! Nítorí Ọlọ́run ti gbẹ̀san yín lára rẹ̀ nítorí ìdájọ́ tí ó gbé ka orí rẹ.”
Rozraduj się nad niem niebo i święci Apostołowie i prorocy; bo się pomścił krzywdy waszej Bóg nad niem.
21 Angẹli alágbára kan sì gbé òkúta kan sókè, ó dàbí ọlọ ńlá, ó sì jù ú sínú Òkun, wí pé: “Báyìí ní a ó fi agbára ńlá bí i Babeli ìlú ńlá ni wó, a kì yóò sì rí i mọ́ láé.
I podniósł jeden Anioł mocny kamień jakoby młyński wielki, i wrzucił go w morze, mówiąc: Takim pędem wrzucony będzie Babilon, miasto ono wielkie, i już więcej nie będzie znaleziony.
22 Àti ohùn àwọn aludùùrù, àti ti àwọn olórin, àti ti àwọn afunfèrè, àti ti àwọn afùnpè, ni a kì yóò sì gbọ́ nínú rẹ mọ́ rara; àti olúkúlùkù oníṣọ̀nà ohunkóhun ni a kì yóò sì rí nínú rẹ mọ́ láé. Àti ìró ọlọ ní a kì yóò sì gbọ́ mọ̀ nínú rẹ láé;
I głos cytrystów, i śpiewaków, i piszczków, i trębaczy więcej w tobie słyszany nie będzie, i żaden rzemieślnik wszelkiego rzemiosła nie znajdzie się więcej w tobie, i grzmot młyna nie będzie więcej słyszany w tobie;
23 Àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà ni kì yóò sì tàn nínú rẹ̀ mọ́ láé; a kì yóò sì gbọ́ ohùn ọkọ ìyàwó àti ti ìyàwó nínú rẹ mọ́ láé: nítorí pé àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni àwọn ẹni ńlá ayé; nítorí pé nípa ọ̀ṣọ́ rẹ̀ ní a fi tàn orílẹ̀-èdè gbogbo jẹ.
I światłość świecy nie będzie się więcej świeciła w tobie, i głos oblubieńca i oblubienicy nie będzie więcej słyszany w tobie; iż kupcy twoi byli wielcy panowie ziemscy, iż czarami twojemi byli zwiedzeni wszystkie narody.
24 Àti nínú rẹ̀ ní a gbé ri ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì, àti ti àwọn ènìyàn mímọ́, àti ti gbogbo àwọn tí a pa lórí ilẹ̀ ayé.”
I w niem znalazła się krew proroków i świętych, i wszystkich, którzy są pobici na ziemi.

< Revelation 18 >