< Revelation 17 >

1 Ọ̀kan nínú àwọn angẹli méje náà tí ó ní ìgò méje wọ̀n-ọn-nì sì wá, ó sì ba mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wá níhìn-ín; èmi ó sì fi ìdájọ́ àgbèrè ńlá ní tí ó jókòó lórí omi púpọ̀ han ọ,
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲍ̅ ⳿ⲛⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲛⲏⲉⲧⲉ ϯⲍ̅ ⳿ⲙⲫⲩⲁⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲁⲧⲁⲙⲟⲕ ⳿ⲉ⳿ⲡϩⲁⲡ ⳿ⲛϯⲛⲓϣϯ ⳿ⲙⲡⲟⲣⲛⲏ ⲑⲏ ⲉⲧϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
2 ẹni tí àwọn ọba ayé bá ṣe àgbèrè, tí a sì fi ọtí wáìnì àgbèrè rẹ̀ pa àwọn tí ń gbé inú ayé.”
ⲃ̅ⲑⲏ ⲉⲧⲁ ⲛⲓⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲛⲉⲙⲁⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣⲡⲟⲣⲛⲉⲩⲓⲛ ⲁⲩⲑⲓϧⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲏⲣⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉⲥⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧϣⲟⲡ ϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ.
3 Ó sì gbé mi nínú ẹ̀mí lọ sí aginjù: mo sì rí obìnrin kan ó jókòó lórí ẹranko aláwọ̀ òdòdó kan tí ó kún fún orúkọ ọ̀rọ̀-òdì, ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲗⲧ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲁϥⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲥϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲟⲩⲑⲏ ⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲕⲟⲕⲕⲟⲥ ⲉϥⲙⲉϩ ⳿ⲛⲣⲁⲛ ⳿ⲛϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲍ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲫⲉ ϩⲓϫⲱϥ ⲛⲉⲙ ⲓ̅ ⳿ⲛⲧⲁⲡ.
4 A sì fi aṣọ elése àlùkò àti aṣọ òdòdó wọ obìnrin náà, a sì fi wúrà àti òkúta iyebíye àti perli ṣe é ní ọ̀ṣọ́, ó ní ago wúrà kan ní ọwọ́ rẹ̀, tí ó kún fún ìríra àti fún ẹ̀gbin àgbèrè rẹ̀;
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁⲥϫⲟⲗϩ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲛϭⲏϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲕⲟⲕⲕⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲥⲟⲓ ⳿ⲛⲓⲉⲃ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲃ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲟⲩⲃ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲱⲛⲓ ⲉⲧⲧⲁⲓⲏⲟⲩⲧ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲁⲛⲁⲙⲏⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲁⲫⲟⲧ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲃ ϧⲉⲛ ⲧⲉⲥϫⲓϫ ⲉϥⲙⲉϩ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲥⲱϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉⲥⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲧⲏⲣϥ.
5 àti níwájú rẹ̀ ni orúkọ kan tí a kọ: Ohun ìjìnlẹ̀ Babeli ńlá ìyá àwọn panṣágà àti àwọn ohun ìríra ayé.
ⲉ̅⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲣⲁⲛ ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϩⲓ ⲧⲉⲥⲧⲉϩⲛⲓ ϫⲉ ⲡⲓⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲑⲃⲁⲃⲩⲗⲱⲛ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲡⲟⲣⲛⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁϥϩⲏⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ.
6 Mo sì rí obìnrin náà mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́, àti ẹ̀jẹ̀ àwọn ajẹ́rìí ikú Jesu ní àmuyó. Nígbà tí mo sì rí i, ẹnu yà mi gidigidi.
ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲥⲑⲁϧⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲥⲛⲟϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡ⳿ⲥⲛⲟϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲙⲁⲣⲧⲩⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ.
7 Angẹli sì wí fún mi pé, “Nítorí kí ni ẹnu ṣe yà ọ́? Èmi ó sọ ti ìjìnlẹ̀ obìnrin náà fún ọ, àti ti ẹranko tí ó gùn, ti ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲛⲏⲓ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲁⲕⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϯⲛⲁⲧⲁⲙⲟⲕ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲩⲥⲧⲏ ⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ ⲉⲧϥⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲫⲏⲉⲧⲉ ϯⲍ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲫⲉ ϩⲓϫⲱϥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲓ̅ ⳿ⲛⲧⲁⲡ.
8 Ẹranko tí ìwọ ri nì, o ti wà, kò sì ṣí mọ́, yóò sì ti inú ọ̀gbun gòkè wá, yóò sì lọ sínú ìparun rẹ. Àwọn olùgbé ayé ti a kọ orúkọ wọn sínú ìwé iye láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, nígbà tí wọn ń wò ẹranko tí o ti wà, tí kò sì ṣí mọ́, tí ó sì ń bọ̀ wá, ẹnu si ya wọn. (Abyssos g12)
ⲏ̅ⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ ⲉⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉϥϣⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥϣⲟⲡ ⲁⲛ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲟⲩⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲛⲁ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ⲉⲉⲣ⳿ϣⲫⲏ ⲣⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧϣⲟⲡ ϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲛⲏⲉⲧⲉ ⲡⲟⲩⲣⲁⲛ ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ⲁⲛ ϩⲓ ⳿ⲡϫⲱⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲛϧ ⲓⲥϫⲉⲛ ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲙⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲉⲩϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛⲏ ϫⲉ ⳿ϥϣⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥϣⲟⲡ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲉⲓ. (Abyssos g12)
9 “Níhìn-ín ni ìtumọ̀ tí o ní ọgbọ́n wà. Orí méje ni òkè ńlá méje ni, lórí èyí tí obìnrin náà jókòó.
ⲑ̅ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϩⲏⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ⳿ⲥⲃⲱ ⲙⲁⲣⲉϥⲕⲁϯ ⳿ⲉϯⲍ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲫⲉ ⳿ⲛⲧⲱⲟⲩ ⲛⲉ ⲉⲣⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲱⲟⲩ.
10 Ọba méje sì ní wọn: àwọn márùn-ún ṣubú, ọ̀kan ń bẹ, ọ̀kan ìyókù kò sì tí ì dé; nígbà tí ó bá sì dé, yóò dúró fún ìgbà kúkúrú.
ⲓ̅ⲛⲁⲓ ⲍ̅ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟ ⲛⲉ ⲡⲓⲉ̅ ⲁⲩϩⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲭⲉⲧ ⳿ϥⲱⲟⲡ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉϥ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉϣⲱⲡ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ϥⲛⲁⲟϩⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ.
11 Ẹranko tí ó sì ti wà, tí kò sì ṣí, òun náà sì ni ẹ̀kẹjọ, ó sì ti inú àwọn méje náà wá, ó sì lọ sí ìparun.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲉⲛⲁϥϣⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ϥϣⲟⲡ ⲁⲛ ⲟⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ϩⲱϥ ⲡⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲍ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ.
12 “Ìwo mẹ́wàá tí ìwọ sì rí ni ọba mẹ́wàá ni wọn, tí wọn kò ì ti gba ìjọba; ṣùgbọ́n wọn gba àṣẹ bí ọba pẹ̀lú ẹranko náà fún wákàtí kan.
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲓ̅ ⳿ⲛⲧⲁⲡ ⲉⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲓ̅ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲟⲩϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲁⲩⲟⲩⲁϩⲟⲩ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ.
13 Àwọn wọ̀nyí ní inú kan, wọ́n yóò sì fi agbára àti ọlá wọn fún ẹranko náà.
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲁⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲉⲣϣⲓϣⲓ ⲧⲟⲩϫⲟⲙ ⲥⲉⲛⲁⲧⲏⲓⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ.
14 Àwọn wọ̀nyí ni yóò si máa bá Ọ̀dọ́-Àgùntàn jagun, Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà yóò sì ṣẹ́gun wọn: nítorí òun ni Olúwa àwọn Olúwa, àti ọba àwọn ọba: àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú rẹ̀, tí a pè, tí a yàn, tí wọ́n sì jẹ́ olóòtítọ́ yóò sì ṣẹ́gun pẹ̀lú.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲁⲓ ⲉⲩ⳿ⲉⲃⲱⲧⲥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓϩⲓⲏⲃ ⲉϥϭⲣⲟ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳪ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧⲑⲁϩⲉⲙ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲱⲧⲡ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲡⲓⲥⲧⲟⲥ.
15 Ó sì wí fún mi pé, “Àwọn omi tí ìwọ ti rí ni, níbi tí àgbèrè náà jókòó, àwọn ènìyàn àti ẹ̀yà àti orílẹ̀ àti onírúurú èdè ni wọ́n.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲏⲓ ϫⲉ ⲛⲓⲙⲱⲟⲩ ⲉⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲉⲣⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲱⲟⲩ ϩⲁⲛⲗⲁⲟⲥ ⲛⲉ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲛⲉⲑⲛⲟⲥ.
16 Àti ìwo mẹ́wàá tí ìwọ rí, àti ẹranko náà, àwọn wọ̀nyí ni yóò kórìíra àgbèrè náà, wọn ó sì sọ ọ́ di ahoro àti ẹni ìhòhò, wọn ó sì jẹ ẹran-ara rẹ̀, wọn ó sì fi iná sun ún pátápátá.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲓ̅ ⳿ⲛⲧⲁⲡ ⲉⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲑⲏⲣⲓⲟⲛ ⲛⲁⲓ ⲉⲩ⳿ⲉⲙⲉⲥⲧⲉ ϯⲡⲟⲣⲛⲏ ⲥⲉⲛⲁϣⲱϥ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲥⲉⲛⲁⲭⲁⲥ ⲉⲥⲃⲏϣ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉⲥⲥⲁⲣⲝ ⲉⲩ⳿ⲉⲟⲩⲟⲙⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲉⲣⲟⲕϩⲥ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲭⲣⲱⲙ.
17 Nítorí Ọlọ́run ti fi sínú ọkàn wọn láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ, láti ní inú kan, àti láti fi ìjọba wọn fún ẹranko náà, títí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yóò fi ṣẹ.
ⲓ̅ⲍ̅ⲫϯ ⲅⲁⲣ ⲁϥⲧⲏⲓⲥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲡⲟⲩϩⲏⲧ ⳿ⲉ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲑⲣⲟⲩϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲉϯ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲙⲡⲓⲑⲏ ⲣⲓⲟⲛ ϣⲁⲧⲟⲩϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
18 Obìnrin tí ìwọ rí ní ìlú ńlá ni, tí ń jẹ ọba lórí àwọn ọba ilẹ̀ ayé.”
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ϯ ⲛⲓϣϯ ⳿ⲙⲃⲁⲕⲓ ⲧⲉ ⲑⲏ ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉⲥ ⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ

< Revelation 17 >