< Revelation 15 >

1 Mo sì rí àmì mìíràn ní ọ̀run tí ó tóbi tí ó sì ya ni lẹ́nu, àwọn angẹli méje tí ó ni àwọn ìyọnu méje ìkẹyìn, nítorí nínú wọn ni ìbínú Ọlọ́run dé òpin.
Then I saw another marvel in Heaven, great and wonderful--there were seven angels bringing seven plagues. These are the last plagues, because in them God's anger has found full expression.
2 Mo sì rí bí ẹni pé, Òkun dígí tí o dàpọ̀ pẹ̀lú iná: àwọn tí ó sì dúró lórí Òkun dígí yìí jẹ́ àwọn ti wọ́n ṣẹ́gun ẹranko náà, àti àwòrán rẹ̀, àti àmì rẹ̀ àti nọ́mbà orúkọ rẹ̀, wọn ní ohun èlò orin Ọlọ́run.
And I saw what seemed to be a sea of glass mingled with fire, and those who had gained the victory over the Wild Beast and over his statue and the number of his name, standing by the sea of glass and having harps which belonged to God.
3 Wọ́n sì ń kọ orin ti Mose, ìránṣẹ́ Ọlọ́run, àti orin ti Ọ̀dọ́-Àgùntàn, wí pé: “Títóbi àti ìyanu ni àwọn iṣẹ́ rẹ, Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè; òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀nà rẹ̀, ìwọ ọba àwọn orílẹ̀-èdè.
And they were singing the song of Moses, God's servant, and the song of the Lamb. Their words were, "Great and wonderful are Thy works, O Lord God, the Ruler of all. Righteous and true are Thy ways, O King of the nations.
4 Ta ni kì yóò bẹ̀rù, Olúwa, tí kì yóò sì fi ògo fún orúkọ rẹ̀? Nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni mímọ́. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ni yóò sì wá, ti yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ, nítorí a ti fi ìdájọ́ rẹ hàn.”
Who shall not be afraid, O Lord, and glorify Thy name? For Thou alone art holy. All nations shall come and shall worship Thee, because the righteousness of all that Thou hast done has been made manifest."
5 Lẹ́yìn náà mo sì wo, sì kíyèsi i, a ṣí tẹmpili àgọ́ ẹ̀rí ní ọ̀run sílẹ̀;
After this, when the doors of the sanctuary of the tent of witness in Heaven were opened, I looked;
6 àwọn angẹli méje náà sì ti inú tẹmpili jáde wá, wọ́n ni ìyọnu méje náà, a wọ̀ wọ́n ní aṣọ ọ̀gbọ̀ funfun ti ń dán, a sì fi àmùrè wúrà dìwọ́n ni oókan àyà.
and there came out of the sanctuary the seven angels who were bringing the seven plagues. The angels were clad in pure, bright linen, and had girdles of gold across their breasts.
7 Àti ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà fi ìgò wúrà méje fún àwọn angẹli méje náà, tí ó kún fún ìbínú Ọlọ́run, ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé. (aiōn g165)
And one of the four living creatures gave the seven angels seven bowls of gold, full of the anger of God who lives until the Ages of the Ages. (aiōn g165)
8 Tẹmpili náà sì kún fún èéfín láti inú ògo Ọlọ́run àti agbára rẹ̀ wá; ẹnikẹ́ni kò sì lè wọ inú tẹmpili náà lọ títí a fi mú ìyọnu méjèèje àwọn angẹli méje náà ṣẹ.
And the sanctuary was filled with smoke from the glory of God and from His power; and no one could enter the sanctuary till the seven plagues brought by the seven angels were at an end.

< Revelation 15 >