< Revelation 15 >

1 Mo sì rí àmì mìíràn ní ọ̀run tí ó tóbi tí ó sì ya ni lẹ́nu, àwọn angẹli méje tí ó ni àwọn ìyọnu méje ìkẹyìn, nítorí nínú wọn ni ìbínú Ọlọ́run dé òpin.
And I beheld another sign in heaven, great and marvelous, seven angels with the seven last plagues; because with them the wrath of God is finished.
2 Mo sì rí bí ẹni pé, Òkun dígí tí o dàpọ̀ pẹ̀lú iná: àwọn tí ó sì dúró lórí Òkun dígí yìí jẹ́ àwọn ti wọ́n ṣẹ́gun ẹranko náà, àti àwòrán rẹ̀, àti àmì rẹ̀ àti nọ́mbà orúkọ rẹ̀, wọn ní ohun èlò orin Ọlọ́run.
And I saw the semblance of a glassy sea, mingled with fire; and standing by this glassy sea, with harps of God, were those who came off conquerors from the beast and from his image and from the cipher of his name.
3 Wọ́n sì ń kọ orin ti Mose, ìránṣẹ́ Ọlọ́run, àti orin ti Ọ̀dọ́-Àgùntàn, wí pé: “Títóbi àti ìyanu ni àwọn iṣẹ́ rẹ, Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè; òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀nà rẹ̀, ìwọ ọba àwọn orílẹ̀-èdè.
They were singing the song of Moses, the slave of God, and the song of the Lamb, saying. "Great and marvelous are thy works, O Lord God, the Almighty! Righteous and true are thy ways, Thou King of kings!
4 Ta ni kì yóò bẹ̀rù, Olúwa, tí kì yóò sì fi ògo fún orúkọ rẹ̀? Nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni mímọ́. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ni yóò sì wá, ti yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ, nítorí a ti fi ìdájọ́ rẹ hàn.”
Who shall not fear, O Lord, And glorify thy name? For thou only art holy. For all the nations shall come and worship before thee; For thy righteous acts have been made evident."
5 Lẹ́yìn náà mo sì wo, sì kíyèsi i, a ṣí tẹmpili àgọ́ ẹ̀rí ní ọ̀run sílẹ̀;
After that I looked, and the sanctuary of the tabernacle of testimony was opened in heaven;
6 àwọn angẹli méje náà sì ti inú tẹmpili jáde wá, wọ́n ni ìyọnu méje náà, a wọ̀ wọ́n ní aṣọ ọ̀gbọ̀ funfun ti ń dán, a sì fi àmùrè wúrà dìwọ́n ni oókan àyà.
and there came out of the sanctuary the seven angels with the seven plagues. They were clothed in white linen, pure and bright, and girt about the breasts with golden girdles.
7 Àti ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà fi ìgò wúrà méje fún àwọn angẹli méje náà, tí ó kún fún ìbínú Ọlọ́run, ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé. (aiōn g165)
And one of the four Living Creatures gave to the seven angels seven golden bowls, full of the wrath of God, who lives forever and ever. (aiōn g165)
8 Tẹmpili náà sì kún fún èéfín láti inú ògo Ọlọ́run àti agbára rẹ̀ wá; ẹnikẹ́ni kò sì lè wọ inú tẹmpili náà lọ títí a fi mú ìyọnu méjèèje àwọn angẹli méje náà ṣẹ.
The sanctuary was filled with smoke from the glory and majesty of God; and no one could enter the sanctuary until the seven plagues of the seven angels were finished.

< Revelation 15 >