< Revelation 12 >
1 Àmì ńlá kan sì hàn ni ọ̀run; obìnrin kan tí a fi oòrùn wọ̀ ní aṣọ, òṣùpá sì ń bẹ lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀, adé oníràwọ̀ méjìlá sì ń bẹ lórí rẹ̀.
Și s-a arătat o mare minune în cer; o femeie îmbrăcată cu soarele, și luna sub picioarele ei, și pe capul ei o coroană cu douăsprezece stele;
2 Ó sì lóyún, ó sì kígbe ni ìrọbí, ó sì wà ni ìrora àti bímọ.
Și, fiind însărcinată, a strigat, fiind în travaliu și în chin ca să nască.
3 Àmì mìíràn sì hàn ní ọ̀run; sì kíyèsi i, dragoni pupa ńlá kan, tí ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá, àti adé méje ní orí rẹ̀.
Și s-a arătat o altă minune în cer; și, iată, un mare dragon roșu, având șapte capete și zece coarne și pe capetele sale șapte coroane.
4 Ìrù rẹ̀ sì wọ́ ìdámẹ́ta àwọn ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run, ó sì jù wọ́n sí ilẹ̀ ayé, dragoni náà sì dúró níwájú obìnrin náà tí ó fẹ́ bímọ, pé nígbà tí o bá bí i, kí òun lè pa ọmọ rẹ̀ jẹ.
Și coada lui trăgea a treia parte a stelelor cerului și le arunca pe pământ; și dragonul a stat în picioare înaintea femeii care era gata să nască, pentru ca să îi mănânce copilul imediat ce va fi născut.
5 Ó sì bi ọmọkùnrin kan tí yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè, a sì gba ọmọ rẹ̀ lọ sókè sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, àti sí orí ìtẹ́ rẹ̀.
Și a născut un copil de parte bărbătească, ce a fost născut pentru a conduce toate națiunile cu un toiag de fier; și copilul a fost răpit la Dumnezeu și la tronul lui.
6 Obìnrin náà sì sálọ sí aginjù, níbi tí a gbé ti pèsè ààyè sílẹ̀ dè é láti ọwọ́ Ọlọ́run wá, pé kí wọ́n máa bọ́ ọ níbẹ̀ ní ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta.
Și femeia a fugit în pustie, unde are pregătit un loc de la Dumnezeu, ca acolo ei să o hrănească o mie două sute șaizeci de zile.
7 Ogun sì ń bẹ ní ọ̀run: Mikaeli àti àwọn angẹli rẹ̀ bá dragoni náà jagun; dragoni sì jagun àti àwọn angẹli rẹ̀.
Și a fost război în cer; Mihail și îngerii lui au luptat împotriva dragonului; și dragonul și îngerii lui au luptat.
8 Wọ́n kò sì lè ṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni a kò sì rí ipò wọn mọ́ ni ọ̀run.
Și nu au învins; nici locul lor nu a mai fost găsit în cer.
9 A sì lé dragoni ńlá náà jáde, ejò láéláé nì, tí a ń pè ni Èṣù, àti Satani, tí ń tan gbogbo ayé jẹ: a sì lé e jù sí ilẹ̀ ayé, a sì lé àwọn angẹli rẹ̀ jáde pẹ̀lú rẹ̀.
Și a fost aruncat afară dragonul cel mare, acel șarpe bătrân, numit Diavolul și Satan, care înșală întreaga lume; a fost aruncat pe pământ și îngerii lui au fost aruncați cu el.
10 Mo sì gbọ́ ohùn ńlá ní ọ̀run, wí pè: “Nígbà yìí ni ìgbàlà dé, àti agbára, àti ìjọba Ọlọ́run wá, àti ọlá àti Kristi rẹ̀. Nítorí a tí le olùfisùn àwọn arákùnrin wa jáde, tí o ń fi wọ́n sùn níwájú Ọlọ́run wa lọ́sàn án àti lóru.
Și am auzit o voce tare, spunând în cer: Acum a venit salvarea și puterea și împărăția Dumnezeului nostru și puterea lui Cristos, pentru că a fost aruncat jos acuzatorul fraților noștri, cel care i-a acuzat înaintea Dumnezeului nostru zi și noapte.
11 Wọ́n sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ nítorí ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn náà, àti nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀rí wọn, wọn kò sì fẹ́ràn ẹ̀mí wọn àní títí dé ikú.
Și l-au învins prin sângele Mielului și prin cuvântul mărturiei lor; și nu și-au iubit viața până la moarte.
12 Nítorí náà ẹ máa yọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, àti ẹ̀yin tí ń gbé inú wọn. Ègbé ni fún ayé àti Òkun; nítorí èṣù sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá ní ìbínú ńlá, nítorí ó mọ̀ pé ìgbà kúkúrú sá ni òun ní.”
Din această cauză, bucurați-vă voi ceruri și cei ce locuiți în ele. Vai locuitorilor pământului și ai mării! Pentru că diavolul a coborât la voi, având furie mare, deoarece știe că mai are doar puțin timp.
13 Nígbà tí dragoni náà rí pé a lé òun lọ sí ilẹ̀ ayé, ó ṣe inúnibíni sì obìnrin tí ó bí ọmọkùnrin náà.
Și când dragonul a văzut că a fost aruncat pe pământ, a persecutat femeia care a născut copilul de parte bărbătească.
14 A sì fi apá ìyẹ́ méjì tí idì ńlá náà fún obìnrin náà, pé kí ó fò lọ sí aginjù, sí ipò rẹ̀, níbi tí a ó gbe bọ ọ fún àkókò kan àti fún àwọn àkókò, àti fún ìdajì àkókò kúrò lọ́dọ̀ ejò náà.
Și femeii i-au fost date două aripi ale unei acvile mari, ca să zboare în pustie, la locul ei, unde este hrănită pentru un timp și timpuri și jumătate a timpului, ascunsă de la fața șarpelui.
15 Ejò náà sì tu omi jáde láti ẹnu rẹ̀ wá bí odò ńlá sẹ́yìn obìnrin náà, kí ó lè fi ìṣàn omi náà gbà á lọ.
Și șarpele a aruncat din gura lui apă ca un potop după femeie, ca să o facă să fie dusă de potop.
16 Ilẹ̀ sì ran obìnrin náà lọ́wọ́, ilẹ̀ sì ya ẹnu rẹ̀, ó sì fi ìṣàn omi náà mú, tí dragoni náà tu jáde láti ẹnu rẹ̀ wá.
Și pământul a ajutat femeia și pământul și-a deschis gura și a înghițit potopul pe care l-a aruncat dragonul din gura sa.
17 Dragoni náà sì bínú gidigidi sí obìnrin náà, ó sì lọ bá àwọn irú-ọmọ rẹ̀ ìyókù jagun, tí wọ́n ń pa òfin Ọlọ́run mọ̀, tí wọn sì di ẹ̀rí Jesu mú, Ó sì dúró lórí iyanrìn Òkun.
Și dragonul a fost furios pe femeie și a mers să facă război cu rămășița seminței ei, cei care țin poruncile lui Dumnezeu și au mărturia lui Isus Cristos.