< Revelation 11 >

1 A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
Manga ɵlqigüq ⱨasidǝk bir ⱪomux berilip, mundaⱪ deyildi: «Barƣin, Hudaning ibadǝthanisi, ⱪurbangaⱨi wǝ u yǝrdǝ ibadǝt ⱪiliwatⱪanlarni ɵlqigin.
2 Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
Lekin ibadǝthanining taxⱪiriⱪi ⱨoylisini ɵlqimǝy ⱪoy, qünki u yǝr yat taipilǝrgǝ berildi, xuning bilǝn muⱪǝddǝs xǝⱨǝr ⱪiriⱪ ikki ay dǝpsǝndǝ ⱪilinidu.
3 Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
Mǝn ikki guwaⱨqimƣa ⱪudrǝt berimǝn, xuning bilǝn ular bɵz kiyim kiyip, wǝⱨiy-bexarǝtlǝrni bir ming ikki yüz atmix kün yǝtküzidu»
4 Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
(bular yǝr-zeminning Rǝbbi aldida turƣan ikki tüp zǝytun dǝrihi wǝ ikki qiraƣdandur).
5 Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
Birǝrsi ularni zǝhimlǝndürmǝkqi bolsa, eƣizliridin ot pürkülüp qiⱪip, düxmǝnlirini yǝp tügitidu. Ularni zǝhimlǝndürmǝkqi bolƣanlar mana xundaⱪ ɵltürülidu.
6 Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
Ular bexarǝt-wǝⱨiyni yǝtküzgǝn künlǝrdǝ yamƣur yaƣdurmasliⱪⱪa asmanni etiwetix ⱪudritikǝ igǝ; sularni ⱪanƣa aylandurux wǝ ⱨǝrhil bala-waba bilǝn yǝr-zeminni haliƣan waⱪitta urux ⱪudritigimu igǝ.
7 Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos g12)
Ularning guwaⱨliⱪ wǝzipisi ayaƣlixixi bilǝn, tegi yoⱪ ⱨangdin qiⱪidiƣan diwǝ ular bilǝn elixidu wǝ ularni yengip ɵltüridu. (Abyssos g12)
8 Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
Jǝsǝtliri roⱨiy jǝⱨǝttin Sodom wǝ Misir dǝp atilidiƣan xu katta xǝⱨǝrning ƣol koqisida yatidu; xu yǝrdǝ ularning Rǝbbimu krestlǝngǝnidi.
9 Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
Ⱨǝr millǝttin, ⱨǝr ⱪǝbilidin wǝ ⱨǝr hil tilda sɵzlixidiƣanlardin, ⱨǝr ǝldin bolƣan adǝmlǝr ularning jǝsǝtlirigǝ üq yerim kün tikilip ⱪaraydu wǝ jǝsǝtlǝrning yǝrlikkǝ ⱪoyuluxiƣa yol ⱪoymaydu.
10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
Yǝr yüzidǝ turuwatⱪanlar ularning bu ⱨalidin huxallinip, tǝbriklixip, bir-birigǝ ⱨǝdiyǝlǝr ǝwǝtixidu; qünki bu ikki pǝyƣǝmbǝr yǝr yüzidikilǝrni ⱪiynaytti.
11 Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
Lekin üq yerim kündin keyin, Hudadin kǝlgǝn ⱨayatliⱪ nǝpisi ikkiylǝngǝ kirdi, ular ornidin put tirǝp turdi; ularƣa ⱪarawatⱪanlarning üstigǝ qong bir ⱪorⱪunq qüxti.
12 Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
Andin ular ikkǝylǝngǝ ǝrxtin kǝlgǝn: — «Bu yaⱪⱪa qiⱪ!» degǝn yuⱪiri bir awazni anglidi; xuning bilǝn ular düxmǝnlirining kɵz aldida bir bulut iqidǝ asmanƣa kɵtürüldi.
13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
Dǝl xu saǝt iqidǝ xiddǝtlik yǝr tǝwrǝx yüz bǝrdi, xǝⱨǝrning ondin biri gumran bolup, yǝttǝ ming kixi ⱨalak boldi. Ⱪalƣanliri dǝkkǝ-dükkigǝ qɵmüp, ǝrxtiki Hudani uluƣlaxti.
14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
Ikkinqi «way» ɵtüp kǝtti; mana, üqinqi «way» kelixkǝ az ⱪaldi.
15 Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn g165)
Andin yǝttinqi pǝrixtǝ kaniyini qaldi; ǝrxtǝ yuⱪiri awazlar anglinip mundaⱪ deyildi: — «Dunyaning padixaⱨliⱪi Pǝrwǝrdigarimiz Wǝ uning Mǝsiⱨining padixaⱨliⱪi boldi, U ǝbǝdil’ǝbǝdgiqǝ ⱨɵküm süridu». (aiōn g165)
16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
Hudaning aldida ɵz tǝhtliridǝ olturƣan yigirmǝ tɵt aⱪsaⱪal yǝrgǝ yiⱪilip bax ⱪoyup, Hudaƣa sǝjdǝ ⱪilip mundaⱪ deyixti: —
17 wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
«Xükürlǝr eytimiz sanga, I bar Bolƣuqi wǝ bar bolƣan Ⱨǝmmigǝ Ⱪadir Pǝrwǝrdigar Huda, Qünki uluƣ ⱪudritingni ⱪolungƣa elip, Ⱨɵkümüngni yürgüzüxkǝ baxliding.
18 Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
Əllǝr ƣǝzǝplǝngǝnidi, Əmdi Sening ƣǝziping yetip kǝldi! Ɵlgǝnlǝrni soraⱪ ⱪilix, Ⱪul-hizmǝtkarliring bolƣan pǝyƣǝmbǝrlǝrni, Muⱪǝddǝs bǝndilǝrni, Tɵwǝn yaki katta bolsun namingdin ⱪorⱪⱪanlarni in’amiƣa igǝ ⱪilix, Yǝr yüzini ⱨalak ⱪilƣanlarni ⱨalak ⱪilix waⱪti kǝldi».
19 A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.
Andin Hudaning ǝrxtiki ibadǝthanisi eqildi wǝ uning ǝⱨdǝ sanduⱪi ibadǝthanida kɵründi; qaⱪmaⱪlar, türlük awazlar, güldürmamilar, yǝr tǝwrǝx wǝ dǝⱨxǝtlik mɵldür boldi.

< Revelation 11 >