< Revelation 11 >

1 A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
Ehapewilwe ilanzi nashi endesa enyapimile. Nabhozewa, “Sogola opime ihekalu elya Ngolobhe na madhabahu, na bhala bhabhaputa mhati yakwe.
2 Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
Lelo osahapime ieneo elya mhati elya wonza huhekalu, afwatanaje bhabhapiye abhantu ebhe Mataifa. Bhakhanye ekhaya enyinza hunsiki owemezi amashomi gane na gabhele.
3 Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
Embabhapele aketi bhane bhabhele amadaraka aga kuwe hunsiki 1, 260, bhailha bhakwete amagunila.”
4 Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
Ebha aketi makwigabhele ege mizeituni nevinala vibhele vyashele vyemeleye pitagalila elya Gosi owe nsi.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
Nkashele omntu yoyonti abhawamule abhavwalaza, isoho lifuma mmalomu gabho nabhavwalazye abhibhi bhabho. Wawonti yawanza abhavwalazye lazima afwe hwidala eli.
6 Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
Ebha aketi bhali nowezo owafunje emwanya aje envula esatonye wakati bhakuva. Bhali ne nguvu owagalulanye amenze abhe lidanda na khome ensi shila shashonti eshikhomo owakati wawonte nabhasongwa.
7 Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos g12)
Owakati na hwaibha bhamalile oshuhuda wabho ola omnyama yafuma hwilende lyeshele selili no malishio aibhomba ibho hwa bhene. Aibhamena nabhagoje. (Abyssos g12)
8 Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
Amabele gabho gaigona mmtaa ogwe mji ogosi (gwashele nashi gukwiziwa Sodoma ne Misri) pashele Ogosi wabho apete amayemba.
9 Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
Hunsiku zitatu ne nusu bhamo bhafumile hwa mwabho bhe bhantu, hwikabela, njango ne kila nsi bhaihwenya amabele gabho na sabhaifumia eshibali eshabhehwe mnkongwa.
10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
Bhala bhebhakhala munsi bhaisha hwabhene nashanjilile, hata natumilane empesya husababu yabho yakuwa bhabhele bhabhapiye amayemba bhala bhabhakheye munsi.
11 Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
Lelo hunsiki zitatu ne nusu omwoi gwe womi afume hwa Ngolobhe ehaibhinji bhape bhaihwemelela humanama gabho. Oowgo ogosi hwaibhinjira bhala bhabhalola.
12 Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
Nantele bhaihomvwa esauti engosi afume amwanya yaibhabhozya, “Enzi ohu!” Bhape bhaibhala pamwanya amwanya hwibhengo, wakati abhibhi bhabho bhaiyenya.
13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
Husala eyo hwaibha nitensya igosi na emo eyekumi yemji yaigwa. Abhantu lufu saba bhaigogwa nitensya bhabhaisagala bhomi bhaiyewa naahupele uluzuvyo Ongolobhe owa mwanya.
14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
Epa lwabho olwabhele pashilile. Enya! Epa lwabho eyatatu ehwenza ninali.
15 Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn g165)
Nantele ontomi owa saba akhomile ipenga lyakwe, ne sauti engosi zya yanjile amwanya naje, “Omwene owa pansi uli umwene wa Gosi wetu owa Kilisiti wakwe. Aitawala wilawila.” (aiōn g165)
16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
Nantele agogolo amalongo gabhele na bhane bhabhali bhakheye mumatengo geshimwene hwitagalila hwa Ngolobhe bhagwiye bhene pansi pensi, hu maso gabho bhasungeme pansi, bhape waputile Ongolobhe.
17 wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
Bhayanjile, “Tafumya ousalifyo wetu huliwe, Gosi Ngolobhe, wotawala amwanya huvyonti, washele ohweli na washele wahali, husababu oyejile enguvu yaho engosi na hwande atawale.
18 Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
Ebhensi bhavitilwe, lakini ilyoyo lyaho lyenzele. Eshi hufishile hwabhafwe alongwe nawe abhapele atumishi bhaho akuwa, bhetehele na bhala bhabhali nowoga witawa lyaho, bhonti bhabhele bhashe sebhahwanziwa hata hashe nabhe nguvu. No wakati waho ufishile owabha nankanye bhala bhashele bhanankanyaga ensi.”
19 A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.
Nantele ihekalu lya Ngolobhe amwanya lya viguliwe ne mopgoso yemalagano gakwe lyabhoneshe muhati lye hekalu yakwe. Hwali nendabho ezyemwanga, ibwago, engulumo ezyelapushe, intesya elensi, na mawe ge mvula.

< Revelation 11 >