< Revelation 11 >

1 A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
I dano mi trzcinę podobną lasce; a Anioł stanął, mówiąc: Wstań, a zmierz kościół Boży i ołtarz, i tych, którzy się modlą w nim.
2 Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
Ale sień, która jest przed kościołem, wyrzuć precz, a nie mierz jej; albowiem dana jest poganom, a miasto święte deptać będą czterdzieści i dwa miesiące.
3 Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
I dam je dwom świadkom moim, którzy prorokować będą tysiąc dwieście i sześćdziesiąt dni, obleczeni będąc w wory.
4 Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
Ci są dwie oliwy i dwa świeczniki, stojące przed obliczem Pana wszystkiej ziemi.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
A jeźliby im kto chciał szkodzić, ogień wynijdzie z ust ich i pożre nieprzyjacioły ich; a jeźliby im kto chciał szkodzić, ten też tak musi być zabity.
6 Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
Ci moc mają zamykać niebo, aby deszcz nie padał za dni proroctwa ich; i mają moc nad wodami, aby je obrócili w krew, i uderzyć ziemię wszelką plagą, ilekroć by chcieli.
7 Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos g12)
A gdy dokończą świadectwa swojego, bestyja, która występuje z przepaści, stoczy z nimi bitwę, a zwycięży ich i pobije ich. (Abyssos g12)
8 Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
A trupy ich leżeć będą na ulicy miasta wielkiego, które nazywają duchownie Sodomą i Egiptem, gdzie też Pan nasz ukrzyżowany jest.
9 Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
I widzieć będą wiele ich z ludzi, z pokolenia i z języków, i z narodów trupy ich przez półczwarta dnia; ale trupów ich nie dopuszczą włożyć w groby:
10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
Owszem mieszkający na ziemi radować się nad nimi będą i weselić; i poślą dary jedni drugim, iż ci dwaj prorocy dręczyli mieszkających na ziemi.
11 Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
A po półczwarta dnia duch żywota od Boga wstąpił w nich i stanęli na nogach swoich, a bojaźń wielka przypadła na tych, którzy ich widzieli.
12 Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
Potem usłyszeli głos wielki z nieba, mówiący im: Wstąpcie sam! I wstąpili na niebo w obłoku, i patrzyli na nich nieprzyjaciele ich.
13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
A w onęż godzinę stało się wielkie trzęsienie ziemi. I upadła dziesiąta część miasta, i pobito w onem trzęsieniu ziemi osób ludzi siedm tysięcy, a drudzy przestraszeni są, i dali chwałę Bogu niebieskiemu.
14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
Biada wtóra przeszła, a oto biada trzecia przyjdzie rychło.
15 Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn g165)
I zatrąbił Anioł siódmy i stały się głosy wielkie na niebie mówiące: Królestwa świata stały się królestwami Pana naszego i Chrystusa jego, i królować będzie na wieki wieków. (aiōn g165)
16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
Tedy oni dwadzieścia i cztery starcy, którzy przed oblicznością Bożą siedzą na stolicach swoich, upadli na oblicza swe i pokłonili się Bogu, mówiąc:
17 wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
Dziękujemy tobie, Panie Boże wszechmogący, któryś jest i któryś był, i który masz przyjść! żeś wziął moc swoję wielką i ująłeś królestwo;
18 Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
I rozgniewały się narody, i przyszedł gniew twój i czas umarłych, aby byli sądzeni i abyś oddał zapłatę sługom twoim, prorokom i świętym, i bojącym się imienia twego, małym i wielkim, i abyś wytracił tych, co psują ziemię.
19 A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.
Tedy otworzony jest kościół Boży na niebie i widziana jest skrzynia przymierza jego w kościele jego; i stały się błyskawice i głosy, i grzmienia, i trzęsienia ziemi i grad wielki.

< Revelation 11 >