< Revelation 11 >
1 A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
Ekkor nádszálhoz hasonló mérővesszőt adtak a kezembe, és ezt mondták: „Kelj fel, és mérd meg Isten templomát és az oltárt, és azokat, akik ott imádkoznak.
2 Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
De az udvart, amely templomon kívül van, hagyd ki, és azt ne mérd meg, mert az a pogányoknak adatott és negyvenkét hónapig taposni fogják a szent várost.
3 Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
Az én két tanúmnak megadom, hogy gyászruhába öltözve prófétáljanak ezerkétszázhatvan napig.“
4 Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
Ők a két olajfa, és a két gyertyatartó, amelyek a föld Ura előtt állnak.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
És ha valaki ártani akar nekik, tűz tör elő szájukból, amely megöli ellenségeiket, és ha valaki ártani akar nekik, annak így kell megöletnie.
6 Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
Ezeknek van hatalmuk arra, hogy bezárják az eget, hogy prófétálásuk idején ne legyen eső. Hatalmuk van a vizek felett, hogy vérré változtassák, és megverjék a földet mindenféle csapással, ahányszor csak akarják.
7 Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos )
És amikor elvégezték bizonyságtételüket, a mélységből feljövő fenevad hadakozik ellenük és legyőzi őket és megöli őket. (Abyssos )
8 Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
Holttestük a nagy város utcáján fekszik, amelyet lelki értelemben Sodomának és Egyiptomnak hívnak, ahol Urunkat is megfeszítették.
9 Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
És a népek és törzsek, és nyelvek és a nemzetek közül valók látják azoknak holttestét három és fél napig, és nem engedik holttestüket sírba tenni.
10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
És a föld lakói örülnek és örvendeznek ennek, és ajándékokat küldenek egymásnak, mert ez a két próféta gyötörte a föld lakosait.
11 Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
De három és fél nap múlva az élet lelke szállt beléjük Istentől, és lábukra álltak és nagy félelem fogta el azokat, akik látták őket.
12 Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
És hangos szózatot hallottak az égből, amely ezt mondta nekik: „Jöjjetek fel ide!“És felmentek egy felhőben az égbe és látták őket ellenségeik.
13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
És abban az órában nagy földrengés támadt, és a város tizedrésze összedőlt, és a földrengés megölt hétezer embert, a többiek pedig megrémültek, és a menny Istenét dicsőítették.
14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
A második jaj elmúlt, íme, a harmadik jaj hamar eljön.
15 Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn )
A hetedik angyal is trombitált és nagy szózatok hangoztak a mennyben, amelyek ezt mondták: „A világ uralma a mi Urunké és az ő Krisztusáé lett, aki örökkön örökké uralkodik“. (aiōn )
16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
És a huszonnégy vén, aki Isten előtt ült királyi székben, arcra esett és imádta Istent,
17 wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
és ezt mondta: „Hálát adunk neked, Urunk, mindenható Isten, aki vagy, aki voltál, és aki eljövendő vagy, mert nagy hatalmadat kezedbe vetted, és a te országlásodat megkezdted.
18 Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
És háborogtak a pogányok, de eljött haragod és a halottak ideje, hogy megítéltessenek, és jutalmat adj a te szolgáidnak, a prófétáknak és a szenteknek, és akik a te nevedet félik, kicsinyeknek és nagyoknak, hogy elpusztítsd azokat, akik a földet pusztítják.“
19 A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.
És megnyílt Isten temploma a mennyben, és látható lett a szövetség ládája a templomban, és villámlás és zúgás és mennydörgés és földindulás és nagy jégeső támadt.