< Revelation 11 >

1 A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
And there was given me a reed like to a rod, and a voice said to me. "Go and measure the temple of God, and the altar, and those who are worshiping therein.
2 Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
But the court which is outside the temple, omit, and do not measure that, for it has been given up to the Gentiles, and they shall tread under foot the Holy City for forty and two months.
3 Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
And I will give power to my two witnesses, and clothed in sackcloth they shall prophesy a thousand two hundred and threescore days.
4 Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
"These are the two olive trees, and the two candlesticks standing before the God of the earth.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
When any one wishes to hurt them, fire comes from their mouth and devours their enemies; and if any man wishes to hurt them, in this manner he must be killed.
6 Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
These have power to shut heaven so that it does not rain in the days of their prophecy; and have power over waters to turn them to blood, and to smite the earth with all plagues, as often as they will.
7 Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos g12)
"And when they shall have finished their testimony, the beast that is coming up out of the bottomless pit will make war with them, and overcome them, and kill them. (Abyssos g12)
8 Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
And their dead bodies lie in the streets of the great city whose mystical name is ‘Sodom’ and ‘Egypt’ - where also their Lord was crucified.
9 Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
For three days and a half men of all peoples, and tribes, and languages, and nations, look upon their dead bodies, and refuse to let their dead bodies be laid in a tomb.
10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
"And those who dwell on the earth are rejoicing over them, and making merry; and they will send gifts to one another; because these two prophets were a torment to those who dwell on the earth.
11 Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
And after three days and a half the breath of life from God entered into them, and they stood on their feet, and great fear fell upon them.
12 Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
And they heard a great voice from heaven saying unto them, "Come up hither," and they went up to heaven on a cloud, while their enemies watched them.
13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
And in that hour there was a great earthquake, and the tenth part of the city fell; and there were killed in the earthquake seven thousand persons; and the rest were frightened and gave glory to the God of heaven.
14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
"The second woe is passed; and there is a third woe soon to follow."
15 Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn g165)
And the seventh angel blew his trumpet; and there followed great voices in heaven, and they said, "THE KINGDOMS OF THIS WORLD ARE BECOME THE KINGDOM OF OUR LORD AND OF HIS CHRIST, AND HE WILL REIGN FOREVER AND EVER." (aiōn g165)
16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
Then the four and twenty Elders who are seated before God on their thrones, fell upon their faces and worshiped God,
17 wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
saying. "We give thee thanks, O Lord God, The Almighty, who art and who wast; For thou hast taken thy great power, And begun to reign.
18 Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
The nations raged, and thy wrath came, And the time for the dead to be judged; The time for rewarding thy slaves, the prophets And the saints, and those who reverence thy name, Both small and great; And the time to destroy those who are destroying the earth."
19 A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.
Then the temple of God in heaven was opened, and the ark of his covenant was seen inside his sanctuary; and there followed lightnings and voices and thunders, and an earthquake, and great hail.

< Revelation 11 >