< Revelation 1 >

1 Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀,
Objawienie Jezusa Chrystusa, które mu dał Bóg, aby okazał sługom swoim rzeczy, które się w rychle dziać mają; a on je oznajmił i posłał przez Anioła swojego słudze swemu Janowi,
2 ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi.
Który świadectwo wydał słowu Bożemu i świadectwu Jezusa Chrystusa, i cokolwiek widział.
3 Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
Błogosławiony, który czyta i ci, którzy słuchają słów proroctwa tego, i zachowują to, co w niem jest napisane; albowiem czas blisko jest.
4 Johanu, Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia: Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀;
Jan siedmiu zborom, które są w Azyi. Łaska wam i pokój niech będzie od tego, który jest i który był, i który przyjść ma; i od siedmiu duchów, którzy są przed oblicznością stolicy jego;
5 àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé. Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,
I od Jezusa Chrystusa, który jest onym świadkiem wiernym, pierworodnym z umarłych i książęciem królów ziemi; który nas umiłował i omył nas z grzechów naszych krwią swoją;
6 tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
I uczynił nas królami i kapłanami Bogu, Ojcu swemu; jemuż niech będzie chwała i moc na wieki wieków. Amen. (aiōn g165)
7 “Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀, gbogbo ojú ni yóò sì rí i, àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”; àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni “yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
Oto idzie z obłokami i ujrzy go wszelkie oko, i ci, którzy go przebili; i narzekać będą przed nim wszystkie pokolenia ziemi. Tak, Amen.
8 “Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
Jam jest Alfa i Omega, początek i koniec, mówi Pan, który jest i który był, i który przyjść ma, on Wszechmogący.
9 Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi.
Ja Jan, którym też jest bratem waszym i uczestnikiem w ucisku i w królestwie, i w cierpliwości Jezusa Chrystusa, byłem na wyspie, którą zowią Patmos, dla słowa Bożego i dla świadectwa Jezusa Chrystusa:
10 Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè,
Byłem w zachwyceniu ducha w dzień Pański i słyszałem za sobą głos wielki jako trąby, mówiący:
11 Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
Jam jest Alfa i Omega, on pierwszy i ostatni; a co widzisz, napisz w księgi i poślij siedmiu zborom, które są w Azyi, do Efezu i do Smyrny, i do Pergamu, i do Tyjatyru, i do Sardów, i do Filadelfii, i do Laodycei.
12 Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje,
I obróciłem się, abym widział on głos, który mówił ze mną; a obróciwszy się, ujrzałem siedm świeczników złotych,
13 àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́.
A w pośrodku onych siedmiu świeczników podobnego Synowi człowieczemu, obleczonego w długą szatę, i przepasanego na piersiach pasem złotym;
14 Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná.
A głowa jego i włosy były białe jako wełna biała, jako śnieg, a oczy jego jako płomień ognia;
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀.
A nogi jego podobne mosiądzowi, jakoby w piecu rozpalone, a głos jego jako głos wielu wód.
16 Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
I miał w prawej ręce swojej siedm gwiazd, a z ust jego wychodził miecz z obu stron ostry, a oblicze jego jako słońce, kiedy jasno świeci.
17 Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn.
A gdym go ujrzał, upadłem do nóg jego jako martwy. I włożył prawą rękę swoję na mię, mówiąc mi: Nie bój się! Jam jest on pierwszy i ostatni,
18 Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́. (aiōn g165, Hadēs g86)
I żyjący; a byłem umarły, a otom jest żywy na wieki wieków. I mam klucze piekła i śmierci. (aiōn g165, Hadēs g86)
19 “Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí;
Napisz te rzeczy, któreś widział i które są, i które się dziać mają napotem.
20 ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.
Tajemnicę onych siedmiu gwiazd, któreś widział w prawej ręce mojej i siedmiu świeczników złotych. Siedm onych gwiazd są Aniołowie siedmiu zborów, a siedm świeczników, któreś widział, jest siedm zborów.

< Revelation 1 >