< Psalms 1 >

1 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà, tí kò rìn ní ìmọ̀ àwọn ènìyàn búburú, ti kò dúró ní ọ̀nà àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, tàbí tí kò sì jókòó ní ibùjókòó àwọn ẹlẹ́gàn.
How happy the man, who hath not walked in the counsel of the lawless, —and, in the way of sinners, hath not stood, and, in the seat of scoffers, hath not sat;
2 Ṣùgbọ́n ayọ̀ inú rẹ̀ wà nínú òfin Olúwa àti nínú òfin rẹ̀ ni ó ń ṣe àṣàrò ní ọ̀sán àti òru.
But, in the law of Yahweh, is his delight, —and, in his law, doth he talk with himself day and night.
3 Ó dàbí igi tí a gbìn sí etí odò tí ń sàn, tí ń so èso rẹ̀ jáde ní àkókò rẹ̀ tí ewé rẹ̀ kì yóò rẹ̀. Ohunkóhun tí ó dáwọ́lé, ni yóò máa yọrí sí rere.
So doth he become like a tree planted by streams of waters, —that yieldeth, its fruit, in its season, whose leaf, also doth not wither, and, whatsoever he doeth, prospereth.
4 Kò le rí bẹ́ẹ̀ fún àwọn ènìyàn búburú! Wọn yóò dàbí ìyàngbò ọkà tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ dànù.
Not so, the lawless, —but as chaff which is driven about by the wind:
5 Nítorí náà àwọn ènìyàn búburú kì yóò le è dìde dúró ní ìdájọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ kì yóò le è dúró ní àwùjọ àwọn olódodo.
For this cause, shall the lawless not stand in the judgment, —nor sinners in the assembly of the righteous.
6 Nítorí Olúwa ń ṣọ́ ọ̀nà àwọn olódodo, ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.
For Yahweh doth acknowledge the way of the righteous; but, the way of the lawless, shall vanish.

< Psalms 1 >