< Psalms 99 >
1 Olúwa jẹ ọba; jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
L'Éternel règne; les peuples tremblent! Il a son trône au-dessus des chérubins; la terre est ébranlée!
2 Olúwa tóbi ní Sioni; Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
L'Éternel est grand dans Sion; Il est élevé au-dessus de tous les peuples.
3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
Qu'on célèbre son nom grand et redoutable: Dieu est saint!
4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo, ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀; ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
Qu'on célèbre la puissance du Roi qui aime la justice. C'est toi, ô Dieu, qui établis le droit; C'est toi qui exerces en Jacob le jugement et la justice.
5 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
Exaltez l'Éternel, notre Dieu; Prosternez-vous devant son marchepied: Dieu est saint!
6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀ Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀ wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.
Moïse et Aaron étaient parmi ses sacrificateurs. Et Samuel parmi ceux qui invoquaient son nom. Ils invoquaient l'Éternel, et il leur répondait;
7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀, wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
Il leur parlait dans la colonne de nuée. Ils ont gardé ses enseignements, Et la loi qu'il leur avait donnée.
8 Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn; ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
Éternel, notre Dieu, tu leur as répondu; Tu fus pour eux un Dieu qui savait leur pardonner. Tout en les punissant de leurs fautes.
9 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀ nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.
Exaltez l'Éternel, notre Dieu, Et prosternez-vous devant sa montagne sainte; Car l'Éternel, notre Dieu, est saint.