< Psalms 99 >

1 Olúwa jẹ ọba; jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
Psaume de David. Le Seigneur a régné, que les peuples exhalent leur colère; il est assis sur les chérubins, que la terre tremble!
2 Olúwa tóbi ní Sioni; Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
Le Seigneur est grand dans Sion; il est élevé au-dessus de tous les peuples.
3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
Exaltez le Seigneur notre Dieu, et adorez l'escabeau de ses pieds; car il est saint.
4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo, ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀; ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
L'honneur du roi aime la justice: tu as établi l'équité; tu as rendu la justice et le jugement en Jacob.
5 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
Exaltez le Seigneur notre Dieu, et adorez l'escabeau de ses pieds; car il est saint.
6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀ Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀ wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.
Moïse et Aaron ont été comptés parmi ses prêtres, et Samuel parmi ceux qui invoquent son nom. Ils invoquaient le Seigneur, et lui les exauçait.
7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀, wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
Il leur parlait du milieu d'une colonne de nuée. Ils gardaient ses témoignages et les commandements qu'il donnait.
8 Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn; ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
Seigneur notre Dieu, tu les as écoutés; ô Dieu, tu leur as été propice, même en toi vengeant de tous leurs desseins.
9 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀ nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.
Exaltez le Seigneur notre Dieu, et adorez-le sur sa montagne sainte; car le Seigneur notre Dieu est saint.

< Psalms 99 >