< Psalms 97 >

1 Olúwa jẹ ọba, jẹ́ kí ayé kí ó yọ̀ jẹ́ kí inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù kí ó dùn.
Yahweh est roi: que la terre soit dans l’allégresse, que les îles nombreuses se réjouissent!
2 Ojú ọ̀run àti òkùnkùn yíká òdodo àti ìdájọ́ ni ó ṣe ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìtẹ́ rẹ̀.
La nuée et l’ombre l’environnent, la justice et l’équité sont la base de son trône.
3 Iná ń jó níwájú rẹ̀. Ó sì ń jó àwọn ọ̀tá rẹ̀ yíkákiri.
Le feu s’avance devant lui, et dévore à l’entour ses adversaires.
4 Ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn ó sì kárí ayé ayé rí i ó sì wárìrì.
Ses éclairs illuminent le monde; la terre le voit et tremble.
5 Òkè gíga yọ́ gẹ́gẹ́ bí ìda níwájú Olúwa, níwájú Olúwa gbogbo ayé.
Les montagnes se fondent, comme la cire, devant Yahweh, devant le Seigneur de toute la terre.
6 Àwọn ọ̀run ròyìn òdodo rẹ̀, gbogbo ènìyàn sì rí ògo rẹ̀.
Les cieux proclament sa justice, et tous les peuples contemplent sa gloire.
7 Gbogbo àwọn tí ń sin ère fínfín ni ojú yóò tì, àwọn tí ń fi ère gbéraga, ẹ máa sìn ín, gbogbo ẹ̀yin ọlọ́run!
Ils seront confondus tous les adorateurs d’images, qui sont fiers de leurs idoles. Tous les dieux se prosternent devant lui.
8 Sioni gbọ́, inú rẹ̀ sì dùn inú àwọn ilé Juda sì dùn, nítorí ìdájọ́ rẹ, Olúwa.
Sion a entendu et s’est réjouie, les filles de Juda sont dans l’allégresse, à cause de tes jugements, Yahweh.
9 Nítorí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ga ju gbogbo ayé lọ ìwọ ni ó ga ju gbogbo òrìṣà lọ.
Car toi, Yahweh, tu es le Très-Haut sur toute la terre, tu es souverainement élevé au dessus de tous les dieux.
10 Jẹ kí gbogbo àwọn tí ó fẹ́ Olúwa, kórìíra ibi, ó pa ọkàn àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́ ó gbà wọ́n ní ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú.
Vous qui aimez Yahweh, haïssez le mal! Il garde les âmes de ses fidèles, il les délivre de la main des méchants.
11 Ìmọ́lẹ̀ tàn sórí àwọn olódodo àti ayọ̀ nínú àlàyé ọkàn.
La lumière est semée pour le juste, et la joie pour ceux qui ont le cœur droit.
12 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olódodo, kí ẹ sì yin orúkọ rẹ̀ mímọ́.
Justes, réjouissez-vous en Yahweh, et rendez gloire à son saint nom.

< Psalms 97 >