< Psalms 96 >
1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
Chantez à l'Éternel un cantique nouveau; chantez à l'Éternel, vous toute la terre!
2 Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
Chantez à l'Éternel; bénissez son nom; annoncez de jour en jour son salut!
3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
Racontez sa gloire parmi les nations, ses merveilles parmi tous les peuples.
4 Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
Car l'Éternel est grand et digne de grandes louanges; il est redoutable par-dessus tous les dieux.
5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
Car tous les dieux des peuples sont des idoles; mais l'Éternel a fait les cieux.
6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
La splendeur et la majesté sont devant lui; la force et la beauté sont dans son sanctuaire.
7 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
Rendez à l'Éternel, familles des peuples, rendez à l'Éternel la gloire et la force!
8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
Rendez à l'Éternel la gloire due à son nom; apportez des offrandes, et entrez dans ses parvis.
9 Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
Prosternez-vous devant l'Éternel avec des ornements sacrés; tremblez devant lui, vous toute la terre!
10 Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
Dites parmi les nations: L'Éternel règne; aussi le monde est ferme et ne chancelle point; il jugera les peuples avec équité.
11 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
Que les cieux se réjouissent, et que la terre tressaille de joie; que la mer retentisse, avec tout ce qu'elle contient!
12 Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
Que les campagnes s'égaient, avec tout ce qui est en elles; que tous les arbres des forêts chantent de joie, devant l'Éternel!
13 Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.
Car il vient; il vient pour juger la terre; il jugera le monde avec justice, et les peuples selon sa fidélité.