< Psalms 96 >

1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
Sing to Yahweh a song new sing to Yahweh O all the earth.
2 Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
Sing to Yahweh bless name his bear news from day to day salvation his.
3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
Recount among the nations glory his among all the peoples wonders his.
4 Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
For [is] great Yahweh and [is] to be praised exceedingly [is] to be feared he above all gods.
5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
For - all [the] gods of the peoples [are] worthless idols and Yahweh [the] heavens he made.
6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Splendor and majesty [are] before him strength and splendor [are] in sanctuary his.
7 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
Ascribe to Yahweh O clans of peoples ascribe to Yahweh glory and strength.
8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
Ascribe to Yahweh [the] glory of name his lift up an offering and come to courts his.
9 Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
Bow down to Yahweh in adornment of holiness tremble from before him O all the earth.
10 Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
Say among the nations - Yahweh he reigns also it is established [the] world not it will be shaken he will judge peoples with uprightness.
11 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
Let them rejoice the heavens and let it be glad the earth let it thunder the sea and what fills it.
12 Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
Let it exult [the] field[s] and all that [is] in it then they will shout for joy all [the] trees of [the] forest.
13 Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.
Before Yahweh - for [he is] coming for [he is] coming to judge the earth he will judge [the] world in righteousness and peoples in faithfulness his.

< Psalms 96 >