< Psalms 96 >

1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
O SING unto the LORD a new song: sing unto the LORD, all the earth.
2 Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
Sing unto the LORD, bless his name; shew forth his salvation from day to day.
3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
Declare his glory among the nations, his marvelous works among all the peoples.
4 Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
For great is the LORD, and highly to be praised: he is to be feared above all gods.
5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
For all the gods of the peoples are idols: but the LORD made the heavens.
6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Honour and majesty are before him: strength and beauty are in his sanctuary.
7 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
Give unto the LORD, ye kindreds of the peoples, give unto the LORD glory and strength.
8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
Give unto the LORD the glory due unto his name: bring an offering, and come into his courts.
9 Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
O worship the LORD in the beauty of holiness: tremble before him, all the earth.
10 Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
Say among the nations, The LORD reigneth: the world also is stablished that it cannot be moved: he shall judge the peoples with equity.
11 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
Let the heavens be glad, and let the earth rejoice; let the sea roar, and the fulness thereof;
12 Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
Let the field exult, and all that is therein; then shall all the trees of the wood sing for joy;
13 Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.
Before the LORD, for he cometh; for he cometh to judge the earth: he shall judge the world with righteousness, and the peoples with his truth.

< Psalms 96 >