< Psalms 95 >
1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
Jőjjetek el, örvendezzünk az Úrnak; vígadozzunk a mi szabadításunk kősziklájának!
2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
Menjünk elébe hálaadással; vígadozzunk néki zengedezésekkel.
3 Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
Mert nagy Isten az Úr, és nagy király minden istenen felül.
4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
A kinek kezében vannak a földnek mélységei, és a hegyeknek magasságai is az övéi.
5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
A kié a tenger, és ő alkotta is azt, és a szárazföldet is az ő kezei formálták.
6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú Olúwa ẹni tí ó dá wa,
Jőjjetek, hajoljunk meg, boruljunk le; essünk térdre az Úr előtt, a mi alkotónk előtt!
7 nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
Mert ő a mi Istenünk, mi pedig az ő legelőjének népei és az ő kezének juhai vagyunk; vajha ma hallanátok az ő szavát.
8 “Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba, àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
Ne keményítsétek meg a ti szíveteket, mint Meribáhnál, mint Maszszáh napján a pusztában:
9 nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò tí wọn wádìí mi, tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
A hol megkisértettek engem a ti atyáitok; próbára tettek engem, jóllehet látták az én cselekedetemet.
10 Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà; mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
Negyven esztendeig bosszankodtam e nemzetségen, és mondám: Tévelygő szívű nép ők, és nem tudják ők az én útamat!
11 Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’”
A kiknek megesküdtem haragomban: Nem mennek be az én nyugalmam helyére.