< Psalms 95 >

1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
Come, sing to Yahweh; sing joyfully to the one who protects us [MET] and saves us!
2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
We should thank him as we come before him, and sing (joyful songs/joyfully) as we praise him.
3 Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
Because Yahweh is the great God, he is a great king [who rules] over all [other] gods.
4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
He rules over the whole earth, from the deepest places/caves to the highest mountains.
5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
The seas are his, because he made them. He is [also] the one who [SYN] formed/made the dry land.
6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú Olúwa ẹni tí ó dá wa,
We should come, worship, and bow down before him. We should kneel before Yahweh, the one who made us.
7 nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
He is our God, and we are the people whom he takes care of [MET]; like sheep [that a shepherd] takes care of. Today, listen to what Yahweh is saying to you.
8 “Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba, àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
He says, “Do not become stubborn [IDM] like [your ancestors] did at Meribah, and like [they did] at Massah in the desert.
9 nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò tí wọn wádìí mi, tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
There your ancestors (wanted to see/tried to determine) if they could do many very evil things [without my punishing them]. Even though they had seen me perform [many] miracles, they tested whether I [would continue to be patient with them].
10 Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà; mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
For 40 years I was angry with those people, and I said, ‘Those people say that they want to please me, but they do things that I detest. They refuse to obey my commands.’
11 Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’”
So because I was very angry, I solemnly said/declared about them: ‘They will never enter [the land of Canaan] where I would have allowed them to rest!’”

< Psalms 95 >