< Psalms 95 >
1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
Halo uh lah. BOEIPA taengah tamhoe uh sih lamtah mamih kah daemnah lungpang ham yuhui uh sih.
2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
Amah mikhmuh ah uemonah neh kun uh sih lamtah laa neh amah taengah yuhui uh sih.
3 Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
BOEIPA tah boeilen Pathen neh pathen boeih sokah boeilen Manghai la om.
4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
Diklai kah a dungnah te a kut ah om tih tlang som rhoek khaw amah hut ni.
5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
Tuitunli te amah hut tih amah ham ni a. saii. Laikoeng khaw amah kut loh a hlinsai.
6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú Olúwa ẹni tí ó dá wa,
Halo uh lah bakop uh sih lamtah bawk uh lah sih. Mamih aka saii BOEIPA hmai ah yoethen uem uh sih.
7 nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
Tihnin a ol te na yaak uh atah amah te mamih kah Pathen la om coeng tih mamih khaw a rhamtlim kah pilnam neh a kut khuikah boiva la n'omuh.
8 “Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba, àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
Khosoek kah Meribah neh Massah tue vaengkah bangla na thinko te mangkhak sak boeh.
9 nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò tí wọn wádìí mi, tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
Teah te na pa rhoek loh kai n'noemcai uh tih ka bisai a hmuh uh lalah kai n'loepdak uh.
10 Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà; mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
Thawnpuei taengah kum likip ka ko-oek tih, “Pilnam he a thinko kho a hmang tih ka longpuei ming uh pawh,” ka ti coeng.
11 Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’”
Te dongah kai kah duemnah khuila a kun uh pawt ham ka thintoek neh ka toemngam thil.