< Psalms 94 >
1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
О Боже помсти, Господи, Боже помсти, з’яви Себе!
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Піднімися, Судде землі, віддай гордим по заслугам!
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Аж доки нечестиві, Господи, доки нечестиві торжествувати будуть?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
Вивергають, промовляють вони пиху, нахваляються всі, хто чинить гріх.
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Народ Твій, Господи, вони вражають ударами й пригнічують Твій спадок.
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
Вдову й приходька вбивають, сироту гублять
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
кажучи: «Не бачить Господь, і не вникає [в це] Бог Якова».
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Схаменіться, невігласи серед народу! Коли ви станете розумнішими, безумці?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Той, Хто насадив вухо, хіба не почує? Чи Той, Хто око створив, не побачить?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Той, Хто народи карає, хіба не докорить? Той, Хто сам людині дає знання?
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
Господь знає думки людини, що вони – марнота.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Блаженний муж, якого Ти наставляєш, Господи, і Законом Твоїм навчаєш його,
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
щоб заспокоїти його у дні лиха, поки буде викопана яма нечестивому!
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
Адже не покине Господь народу Свого й спадку Свого не полишить.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Суд знову стане справедливим, і підуть услід за ним усі, праведні серцем.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Хто стане за мене проти злодіїв? Хто стоятиме за мене проти тих, що чинять гріх?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Якби Господь не був допомогою моєю, то оселилася б душа моя в [країні] мовчання.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Коли сказав я: «Хитається нога моя», милість Твоя, Господи, підтримала мене.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
Коли тривожні думки множаться в нутрі моєму, Твоя втіха збадьорює мою душу.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Хіба може мати щось спільне з Тобою престол загибелі, що діє всупереч постанові [Закону]?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Натовпом тиснуть вони на душу праведника, і кров невинну засуджують [на страту].
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
Але Господь став моєю твердинею, і Бог мій – скеля мого притулку.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
Він поверне проти них їхні власні гріхи і їхніми ж злодійствами знищить їх; знищить їх Господь, Бог наш.