< Psalms 94 >

1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Boże zemsty, PANIE Boże zemsty, objaw się!
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Powstań, Sędzio [całej] ziemi, odpłać pysznym.
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Jak długo niegodziwi, PANIE, jak długo niegodziwi będą się radować?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
[Jak długo] będą pleść, mówić zuchwale i chełpić się wszyscy czyniący nieprawość?
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Depczą twój lud, PANIE, i gnębią twoje dziedzictwo.
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
Mordują wdowy i przybysza, zabijają sieroty.
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
I mówią: PAN tego nie widzi, nie dostrzega tego Bóg Jakuba.
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Zrozumcie, nierozumni wśród ludu! A wy, głupcy, kiedy zmądrzejecie?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Czy ten, który wszczepił ucho, nie słyszy? Czy ten, który ukształtował oko, nie widzi?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Czy ten, który chłoszcze narody, nie będzie karał? [Ten], który uczy człowieka wiedzy, [czy nie wie]?
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
PAN zna myśli ludzkie; [wie], że są marnością.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Błogosławiony mąż, którego ty chłoszczesz, PANIE, i uczysz go twym prawem;
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
Aby dać mu odpocząć od złych dni, aż będzie wykopany dół dla niegodziwego.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
PAN bowiem nie odrzuci swego ludu i nie opuści swego dziedzictwa.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Ale sąd powróci do sprawiedliwości, a wszyscy serca prawego [pójdą] za nim.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Któż stanie przy mnie przeciwko złoczyńcom? Kto ujmie się za mną przeciwko czyniącym nieprawość?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Gdyby PAN nie przyszedł mi z pomocą, moja dusza przebywałaby w milczeniu.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Gdy powiedziałem: Moja noga się chwieje, twoje miłosierdzie, PANIE, mnie wsparło.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
W niezliczonych myślach mego serca twoje pociechy rozweselają moją duszę.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Czy sprzymierzy się z tobą tron nieprawości, który wyrządza krzywdę pod pozorem prawa?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Zbierają się przeciw duszy sprawiedliwego i krew niewinną potępiają.
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
Lecz PAN jest moją twierdzą, mój Bóg – skałą mojej ucieczki.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
On obróci przeciwko nim ich nieprawość i za ich zło ich wytraci; wytraci ich PAN, nasz Bóg.

< Psalms 94 >