< Psalms 94 >

1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Boże pomst! Panie Boże pomst! rozjaśnij się!
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Podnieś się, o Sędzio wszystkiej ziemi! a daj zapłatę pysznym.
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Dokądże niepobożni, Panie! dokądże niepobożni radować się będą?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
Długoż będą świegotać i hardzie mówić, chlubiąc się wszyscy, którzy czynią nieprawość?
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Lud twój, Panie! trzeć, a dziedzictwo twoje trapić?
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
Wdowy i przychodniów mordować? a sierotki zabijać?
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
Mówiąc: Nie widzi tego Pan, ani tego rozumie Bóg Jakóbowy.
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Zrozumicież, o wy bydlęcy między ludźmi! a wy szaleni kiedyż zrozumiecie?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Izali ten, który szczepił ucho, nie słyszy? i który ukształtował oko, izali nie widzi?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Izali ten, który ćwiczy narody, nie będzie karał? który uczy człowieka umiejętności.
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
Pan zna myśli ludzkie, iż są szczerą marnością.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Błogosławiony jest mąż, którego ty ćwiczysz, Panie! a zakonu twego uczysz go.
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
Abyś mu sprawił pokój od złych dni, ażby był wykopany dół niezbożnikowi.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
Albowiem, nie opuści Pan ludu swego, a dziedzictwa swego nie zaniecha.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Ale aż ku sprawiedliwości obróci się sąd, a za nim wszyscy serca uprzejmego.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Któżby się był zastawił za mną przeciwko złośnikom? ktoby się był ujął o mnie przeciwko tym, którzy czynią nieprawość?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
By mi był Pan nie przybył na pomoc, małoby była nie mieszkała dusza moja w milczeniu.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Jużem był rzekł: Zachwiała się noga moja; ale miłosierdzie twoje, o Panie! zatrzymało mię.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
W wielkości utrapienia mego, we wnętrznościach moich, pociechy twoje rozweselały duszę moję.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Izali z tobą towarzyszy stolica nieprawości tych, którzy stanowią krzywdę miasto prawa?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Którzy się zbierają przeciwko duszy sprawiedliwego, a krew niewinną potępiają?
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
Ale Pan jest twierdzą moją, a Bóg mój skałą ufności mojej.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
Onci obróci na nich nieprawość ich, a dla złości ich wytraci ich; wytraci ich Pan, Bóg nasz.

< Psalms 94 >