< Psalms 94 >

1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Megtorlásnak Istene, Örökkévaló, megtorlásnak Istene, jelenj meg!
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Emelkedjél, birája a földnek, hárítsd vissza tettüket a gőgösökre.
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Meddig fognak a gonoszok, oh Orökkévaló, meddig fognak a gonoszok újjongani?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
Bugyogtatnak, beszélnek daczosat, kérkednek mind a jogtalanságot cselekvők.
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Népedet, Örökkévaló, zúzzák, és birtokodat sanyargatják;
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
özvegyet és jövevényt ölnek és árvákat gyilkolnak.
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
S azt mondták Nem látja Jáh s nem ügyel rá Jákób Istene.
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Ügyeljetek, ti oktalanok a nép közt, s ti balgák, mikor tértek észre?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Vajon a ki fület plántál, nem hall-e, avagy a ki szemet alkot, nem 1át-e?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Vajon a ki nemzeteket fenyít, nem büntet-e, ő, ki az embert tudásra tanítja?
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
Az Örökkévaló tudja az ember gondolatait, hogy hiábavalóság azok.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Boldog a férfi, kit megfenyítsz, Jáh, és tanodra taníted;
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
hogy nyugtot adj neki bajnak napjaitól, míg megásatik a gonosznak a verem.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
Mert nem veti el népét az Örökkévaló, s birtokát nem hagyja el.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Mert igazsághoz tér vissza az ítélet, és utána mennek mind az egyenesszívüek.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Ki támad mellém a gonosztevők ellen, ki áll oda mellém a jogtalanságot cselekvők ellen?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Hogyha nem volna az Örökkévaló segítségül nekem, kevés híján sír csendjében lakott volna a lelkem.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Ha azt mondtam: megingott a lábam – szereteted, oh Örökkévaló támogat engem.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
Mikor sok a tépelődés én bennem, a te vigasztalásaid vidámítják föl lelkemet.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Vajon társul-e veled a veszedelmek trónja, az a ki bajt alkot a törvény ellenére?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Összecsődülnek az igaznak lelke ellen, s az ártatlan vért kárhoztatják.
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
De nekem az Örökkévaló mentsvárul lett, és Istenem menedékem sziklájává;
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
s visszahárította rájuk gazságukat s rosszaságukban megsemmisíti őket, megsemmisíti őket az Örökkévaló, a mi Istenünk.

< Psalms 94 >