< Psalms 94 >
1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Yahvé, Dieu à qui appartient la vengeance, toi, Dieu à qui appartient la vengeance, brille.
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Lève-toi, juge de la terre. Rendez aux fiers ce qu'ils méritent.
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Yahvé, jusqu'à quand les méchants, combien de temps les méchants triompheront-ils?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
Ils répandent des paroles arrogantes. Tous les méchants se vantent.
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Ils brisent ton peuple en morceaux, Yahvé, et afflige ton héritage.
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
Ils tuent la veuve et l'étranger, et assassinent les orphelins.
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
Ils disent: « Yah ne verra pas, le Dieu de Jacob n'en tiendra pas compte non plus. »
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Réfléchissez, vous qui êtes insensés parmi le peuple; Vous êtes fous, quand serez-vous sages?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Celui qui a implanté l'oreille, n'entendra-t-il pas? Celui qui a formé l'œil, ne verra-t-il pas?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Celui qui discipline les nations, ne punira-t-il pas? Celui qui enseigne à l'homme sait.
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
Yahvé connaît les pensées de l'homme, qu'ils sont futiles.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Béni soit l'homme que tu disciplines, Yah, et enseigner à partir de ta loi,
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
afin que tu lui donnes du repos pendant les jours d'adversité, jusqu'à ce que la fosse soit creusée pour les méchants.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
Car Yahvé ne rejette pas son peuple, il n'abandonnera pas non plus son héritage.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Car le jugement reviendra à la justice. Tous ceux qui ont le cœur droit le suivront.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Qui se lèvera pour moi contre les méchants? Qui se lèvera pour moi contre les malfaiteurs?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Si Yahvé n'avait pas été mon secours, mon âme aurait vite vécu dans le silence.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Quand je disais: « Mon pied glisse! » Ta bonté, Yahvé, m'a soutenu.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
Dans la multitude de mes pensées au dedans de moi, tes réconforts ravissent mon âme.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Le trône de la méchanceté n'aura pas de communion avec vous, qui entraîne des méfaits par la loi?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Ils s'assemblent contre l'âme du juste, et condamner le sang innocent.
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
Mais Yahvé a été ma haute tour, mon Dieu, le rocher de mon refuge.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
Il a fait retomber sur eux leur propre iniquité, et les exterminera dans leur propre méchanceté. Yahvé, notre Dieu, les exterminera.