< Psalms 94 >

1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
HERRE, du Hævnens Gud, du Hævnens Gud, træd frem i Glans;
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
staa op, du Jordens Dommer, øv Gengæld mod de hovmodige!
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Hvor længe skal gudløse, HERRE, hvor længe skal gudløse juble?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
De fører tøjlesløs Tale, hver Udaadsmand ter sig som Herre;
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
de underkuer, o HERRE, dit Folk og undertrykker din Arvelod;
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
de myrder Enke og fremmed, faderløse slaar de ihjel;
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
de siger: »HERREN kan ikke se, Jakobs Gud kan intet mærke!«
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Forstaa dog, I Taaber blandt Folket! Naar bliver I kloge, I Daarer?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Skulde han, som plantede Øret, ej høre, han, som dannede Øjet, ej se?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Skulde Folkenes Tugtemester ej revse, han som lærer Mennesket indsigt?
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
HERREN kender Menneskets Tanker, thi de er kun Tomhed.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Salig den Mand, du tugter, HERRE, og vejleder ved din Lov
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
for at give ham Ro for onde Dage, indtil der graves en Grav til den gudløse;
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
thi HERREN bortstøder ikke sit Folk og svigter ikke sin Arvelod.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Den retfærdige kommer igen til sin Ret, en Fremtid har hver oprigtig af Hjertet.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Hvo staar mig bi mod Ugerningsmænd? hvo hjælper mig mod Udaadsmænd?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Var HERREN ikke min Hjælp, snart hviled min Sjæl i det stille.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Naar jeg tænkte: »Nu vakler min Fod«, støtted din Naade mig, HERRE;
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
da mit Hjerte var fuldt af ængstede Tanker, husvaled din Trøst min Sjæl.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Staar du i Pagt med Fordærvelsens Domstol, der skaber Uret i Lovens Navn?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
Jager de end den retfærdiges Liv og dømmer uskyldigt Blod,
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
HERREN er dog mit Bjærgested, min Gud er min Tilflugtsklippe;
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
han vender deres Uret imod dem selv, udsletter dem for deres Ondskab; dem udsletter HERREN vor Gud.

< Psalms 94 >