< Psalms 94 >
1 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Herre! Gud, hvem Hævnen hører til, Gud, hvem Hævnen hører til, aabenbar dig herligt!
2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
Rejs dig, du Jordens Dommer! bring Gengældelse over de hovmodige.
3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
Herre! hvor længe skulle de ugudelige, hvor længe skulle de ugudelige fryde sig?
4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
De udgyde en Strøm af Ord, de føre fræk Tale; de rose sig selv, alle de, som øve Uret.
5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Herre! de knuse dit Folk og plage din Arv.
6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
De ihjelslaa Enken og den fremmede og myrde de faderløse.
7 Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
Og de sagde: Herren ser det ikke, og Jakobs Gud mærker det ikke.
8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Giver dog Agt, I ufornuftige iblandt Folket! og I Daarer! naar ville I blive kloge?
9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
Mon han, som plantede Øret, ikke skulde høre? eller mon han, som dannede Øjet, ikke skulde se?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
Mon han, som advarer Hedningerne, ikke skulde straffe? han, som lærer et Menneske Kundskab!
11 Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
Herren kender Menneskenes Tanker, thi de ere Forfængelighed.
12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
Salig er den Mand, som du, Herre! advarer, og den, du underviser ud af din Lov
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
for at skaffe ham Hvile fra de onde Dage, indtil der bliver gravet en Grav for den ugudelige.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
Thi Herren skal ikke opgive sit Folk og ej forlade sin Arv.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Thi Retten skal vende tilbage til Retfærdighed, og alle de oprigtige af Hjertet skulle efterfølge den.
16 Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
Hvo staar hos mig imod de onde? hvo stiller sig hos mig imod dem, som gøre Uret?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
Dersom Herren ikke havde været min Hjælp, da havde min Sjæl paa lidet nær boet i det stille.
18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
Der jeg sagde: Min Fod snublede, da opholdt, o Herre! din Miskundhed mig.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
Der jeg havde mange Bekymringer i mit Inderste, da forlystede din Trøst min Sjæl.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
Skulde Ondskabens Trone have Samkvem med dig? den, som gør Uret tvært imod, hvad Ret er?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
De slaa sig sammen skarevis imod en retfærdigs Sjæl, og de fordømme uskyldigt Blod.
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
Men Herren blev mig en Befæstning, og min Gud blev mig en Tilflugts Klippe.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
Og han har ladet deres Uret falde tilbage over dem og skal udrydde dem for deres Ondskab; Herren vor Gud skal udrydde dem.