< Psalms 92 >
1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
Псалом песни, в день субботный. Благо есть исповедатися Господеви и пети имени Твоему, Вышний:
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
возвещати заутра милость Твою и истину Твою на всяку нощь,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
в десятоструннем псалтири с песнию в гуслех.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Яко возвеселил мя еси, Господи, в творении Твоем, и в делех руку Твоею возрадуюся.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
Яко возвеличишася дела Твоя, Господи: зело углубишася помышления Твоя.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
Муж безумен не познает, и неразумив не разумеет сих.
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
Внегда прозябоша грешницы яко трава, и проникоша вси делающии беззаконие, яко да потребятся в век века:
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
Ты же вышний во век, Господи.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
Яко се, врази Твои, Господи, яко се, врази Твои погибнут, и разыдутся вси делающии беззаконие.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
И вознесется яко единорога рог мой, и старость моя в елеи мастите:
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
и воззре око мое на враги моя, и востающыя на мя лукавнующыя услышит ухо мое.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
Праведник яко финикс процветет: яко кедр, иже в Ливане, умножится.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Насаждени в дому Господни во дворех Бога нашего процветут:
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
еще умножатся в старости мастите, и благоприемлюще будут.
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
Да возвестят, яко прав Господь Бог наш, и несть неправды в Нем.