< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
Un psalm sau o cântare pentru ziua de sabat. Este un lucru bun să aduci mulțumiri DOMNULUI și să cânți laude numelui tău, cel Preaînalt,
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
Să se arate bunătatea ta iubitoare dimineața și credincioșia ta în fiecare noapte;
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
Pe un instrument cu zece coarde și pe psalterion, pe harpa cu sunet solemn.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Pentru că tu, DOAMNE, m-ai înveselit prin lucrarea ta, voi triumfa în lucrările mâinilor tale.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
DOAMNE, cât de mari sunt lucrările tale! Și gândurile tale sunt foarte adânci.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
Un om neghiob nu știe; niciun prost nu înțelege aceasta.
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
Când cel stricat răsare ca iarba și când toți lucrătorii nelegiuirii înfloresc, este pentru a fi nimiciți pentru totdeauna,
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
Dar tu, DOAMNE, ești cel mai înalt pentru totdeauna.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
Căci, iată, dușmanii tăi, DOAMNE, căci, iată, dușmanii tăi vor pieri; toți lucrătorii nelegiuirii vor fi împrăștiați.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
Dar tu vei înălța cornul meu ca al unicornului, voi fi uns cu untdelemn proaspăt.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
Ochiul meu de asemenea va vedea dorința mea împlinită asupra dușmanilor mei și urechile mele vor auzi dorința mea împlinită asupra celor stricați ce se ridică împotriva mea.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
Cel drept va înflori ca palmierul, va crește ca un cedru în Liban.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Cei sădiți în casa DOMNULUI vor înflori în curțile Dumnezeului nostru.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
Ei vor aduce rod și la bătrânețe; vor fi grași și înfloritori;
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
Ca să arate că DOMNUL este integru; el este stânca mea și nu este nedreptate în el.

< Psalms 92 >