< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
Psaume. Cantique pour le jour du sabbat. Il est bon de louer Yahweh, et de célébrer ton nom, ô Très-Haut,
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
de publier le matin ta bonté, et ta fidélité pendant la nuit,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
sur l’instrument à dix cordes et sur le luth, avec les accords de la harpe.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Tu me réjouis, Yahweh, par tes œuvres, et je tressaille devant les ouvrages de tes mains.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
Que tes œuvres sont grandes, Yahweh, que tes pensées sont profondes!
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
L’homme stupide n’y connaît rien, et l’insensé n’y peut rien comprendre.
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
Quand les méchants croissent comme l’herbe, et que fleurissent tous ceux qui font le mal, c’est pour être exterminés à jamais.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
Mais toi, tu es élevé pour l’éternité, Yahweh!
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
Car voici que tes ennemis, Yahweh, voici que tes ennemis périssent, tous ceux qui font le mal sont dispersés.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
Et tu élèves ma corne, comme celle du buffle, je suis arrosé avec une huile fraîche.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
Mon œil se plaît à contempler mes ennemis, et mon oreille à entendre les méchants qui s’élèvent contre moi.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
Le juste croîtra comme le palmier, il s’élèvera comme le cèdre du Liban.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Plantés dans la maison de Yahweh, ils fleuriront dans les parvis de notre Dieu.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
Ils porteront encore des fruits dans la vieillesse; ils seront pleins de sève et verdoyants,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
pour proclamer que Yahweh est juste: il est mon rocher, et il n’y a pas en lui d’injustice.

< Psalms 92 >