< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
Un psaume. Un chant pour le jour du sabbat. C'est une bonne chose que de rendre grâce à Yahvé, pour chanter les louanges de ton nom, le Très-Haut,
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
pour proclamer ta bonté dès le matin, et votre fidélité chaque nuit,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
avec le luth à dix cordes, avec la harpe, et avec la mélodie de la lyre.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Car toi, Yahvé, tu m'as réjoui par ton œuvre. Je triompherai dans les œuvres de tes mains.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
Que tes œuvres sont grandes, Yahvé! Vos pensées sont très profondes.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
Un homme insensé ne sait pas, Un imbécile ne le comprend pas non plus:
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
Les méchants poussent comme l'herbe, et tous les malfaiteurs prospèrent, ils seront détruits à jamais.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
Mais toi, Yahvé, tu es en haut pour toujours.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
Car voici tes ennemis, Yahvé, car voici que vos ennemis vont périr. Tous les malfaiteurs seront dispersés.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
Mais tu as élevé ma corne comme celle du bœuf sauvage. Je suis oint d'une huile fraîche.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
Mon œil a aussi vu mes ennemis. Mes oreilles ont entendu parler des méchants ennemis qui se dressent contre moi.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
Le juste fleurira comme le palmier. Il grandira comme un cèdre au Liban.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Ils sont plantés dans la maison de l'Éternel. Ils s'épanouiront dans les cours de notre Dieu.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
Ils produiront encore des fruits dans leur vieillesse. Ils seront pleins de sève et de vert,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
pour montrer que Yahvé est droit. Il est mon rocher, et il n'y a pas d'injustice en lui.

< Psalms 92 >