< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
A Melody, a Song, For the Sabbath-day. It is good to give thanks to Yahweh, And to sing praises unto thy Name, O Most High;
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
To declare, in the morning, thy lovingkindness, And thy faithfulness at night;
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
Upon an instrument of ten strings, and upon a harp, With resounding music on the lyre.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
For thou hast made me glad, O Yahweh, in thy doing, In the works of thy hands, will I shout for joy.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
How great have grown thy works, Yahweh, [How] very deep are laid thy plans!
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
A man that is brutish, cannot know, And, a dullard, cannot discern this: —
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
When the lawless do thrive like grass, And all the workers of iniquity have blossomed, It is that they may be destroyed for ever.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
But, thou, shalt be on high age-abidingly, O Yahweh.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
For lo! thine enemies, Yahweh, For lo! thine enemies, shall perish, They shall be scattered—all the workers of iniquity;
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
But thou wilt exalt, as [those of] the buffalo, my horn, I have been anointed, with fresh oil.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
So hath mine eye descried them who were lying in wait for me, —Of my wicked assailants, mine ears, shall hear.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
The righteous, like the palm-tree, shall thrive, Like the cedar in Lebanon, shall he grow;
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
They who are planted in the house of Yahweh, In the courts of our God, shall flourish;
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
Still shall they bear fruit in old age, Vigorous and fresh, shall they be:
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
To declare that upright is Yahweh, My Rock, and no perversity in him.

< Psalms 92 >