< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
It is a good thing to give thanks unto the LORD, and to sing praises unto thy Name, O most High:
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
To show forth your loving kindness in the morning, and your faithfulness every night,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
On an instrument of ten strings, and on the psaltery; on the harp with a solemn sound.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
For you, LORD, have made me glad through your work: I will triumph in the works of your hands.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
O LORD, how great are your works! and your thoughts are very deep.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
A brutish man knows not; neither does a fool understand this.
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
When the wicked spring as the grass, and when all the workers of iniquity do flourish; it is that they shall be destroyed for ever:
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
But you, LORD, are most high for ever more.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
For, see, your enemies, O LORD, for, see, your enemies shall perish; all the workers of iniquity shall be scattered.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
But my horn shall you exalt like the horn of an unicorn: I shall be anointed with fresh oil.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
My eye also shall see my desire on my enemies, and my ears shall hear my desire of the wicked that rise up against me.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
The righteous shall flourish like the palm tree: he shall grow like a cedar in Lebanon.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Those that be planted in the house of the LORD shall flourish in the courts of our God.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
They shall still bring forth fruit in old age; they shall be fat and flourishing;
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
To show that the LORD is upright: he is my rock, and there is no unrighteousness in him.

< Psalms 92 >