< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
A Psalme or song for the Sabbath day. It is a good thing to praise the Lord, and to sing vnto thy Name, O most High,
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
To declare thy louing kindenesse in the morning, and thy trueth in the night,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
Vpon an instrument of tenne strings, and vpon the viole with the song vpon the harpe.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
For thou, Lord, hast made mee glad by thy workes, and I wil reioyce in the workes of thine handes.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
O Lord, how glorious are thy workes! and thy thoughtes are very deepe.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
An vnwise man knoweth it not, and a foole doeth not vnderstand this,
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
(When the wicked growe as the grasse, and all the workers of wickednesse doe flourish) that they shall be destroyed for euer.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
But thou, O Lord, art most High for euermore.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
For loe, thine enemies, O Lord: for loe, thine enemies shall perish: all the workers of iniquitie shall be destroyed.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
But thou shalt exalt mine horne, like the vnicornes, and I shalbe anoynted with fresh oyle.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
Mine eye also shall see my desire against mine enemies: and mine eares shall heare my wish against the wicked, that rise vp against me.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
The righteous shall flourish like a palme tree, and shall grow like a Cedar in Lebanon.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Such as bee planted in the house of the Lord, shall flourish in the courtes of our God.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
They shall still bring foorth fruite in their age: they shall be fat and flourishing,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
To declare that the Lord my rocke is righteous, and that none iniquitie is in him.

< Psalms 92 >