< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
A Canticle Psalm. On the day of the Sabbath. It is good to confess to the Lord and to sing psalms to your name, O Most High:
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
to announce your mercy in the morning, and your truth throughout the night,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
upon the ten strings, upon the psaltery, with a canticle, upon stringed instruments.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
For you, O Lord, have delighted me with your doings, and I will exult in the works of your hands.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
How great are your works, O Lord! Your thoughts have been made exceedingly deep.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
A foolish man will not know these things, and a senseless one will not understand:
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
when sinners will have risen up like grass, and when all those who work iniquity will have appeared, that they shall pass away, age after age.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
But you, O Lord, are the Most High for all eternity.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
For behold your enemies, O Lord, for behold your enemies will perish, and all those who work iniquity will be dispersed.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
And my horn will be exalted like that of the single-horned beast, and my old age will be exalted in fruitful mercy.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
And my eye has looked down upon my enemies, and my ear will hear of the malignant rising up against me.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
The just one will flourish like the palm tree. He will be multiplied like the cedar of Lebanon.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Those planted in the house of the Lord will flourish in the courts of the house of our God.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
They will still be multiplied in a fruitful old age, and they will endure well,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
so that they may announce that the Lord our God is righteous and that there is no iniquity in him.

< Psalms 92 >