< Psalms 92 >
1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
A Psalm. A song for the Sabbath day. It is good to praise the LORD, and to sing praises to Your name, O Most High,
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
to proclaim Your loving devotion in the morning and Your faithfulness at night
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
with the ten-stringed harp and the melody of the lyre.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
For You, O LORD, have made me glad by Your deeds; I sing for joy at the works of Your hands.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
How great are Your works, O LORD, how deep are Your thoughts!
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
A senseless man does not know, and a fool does not understand,
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
that though the wicked sprout like grass, and all evildoers flourish, they will be forever destroyed.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
But You, O LORD, are exalted forever!
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
For surely Your enemies, O LORD, surely Your enemies will perish; all evildoers will be scattered.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
But You have exalted my horn like that of a wild ox; with fine oil I have been anointed.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
My eyes see the downfall of my enemies; my ears hear the wailing of my wicked foes.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
The righteous will flourish like a palm tree, and grow like a cedar in Lebanon.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Planted in the house of the LORD, they will flourish in the courts of our God.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
In old age they will still bear fruit; healthy and green they will remain,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
to proclaim, “The LORD is upright; He is my Rock, and in Him there is no unrighteousness.”