< Psalms 90 >

1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Gospod, ti si bil naše bivališče za vse rodove.
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Preden so bile rojene gore, oziroma kadarkoli si oblikoval zemljo in zemeljski [krog], celo od večnosti do večnosti, si ti Bog.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Človeka obračaš k uničenju in praviš: »Vrnite se, vi človeški otroci.«
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Kajti tisoč let v tvojem pogledu je samo kakor včerajšnji dan, ki je minil in kakor straža v noči.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Odnašaš jih proč kakor s poplavo; oni so kakor spanec. Zjutraj so podobni travi, ki raste.
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
Zjutraj cveti in raste, zvečer je odrezana in ovene.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Kajti použiti smo s tvojo jezo in s tvojim besom smo zbegani.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Predse si postavil naše krivičnosti, naše skrite grehe v svetlobo svojega obličja.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Kajti vsi naši dnevi so minili v tvojem besu. Svoja leta smo preživeli kakor zgodbo, ki je povedana.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
Dni naših let je sedemdeset let in če jih je zaradi razloga moči osemdeset let, je vendarle njihova moč trud in bridkost, kajti to je kmalu odrezano in mi odletimo.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Kdo pozna moč tvoje jeze? Celó glede na tvoj strah, tak je tvoj bes.
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Zaradi tega nas uči šteti naše dneve, da bomo svoja srca lahko posvetili modrosti.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Vrni se, oh Gospod, doklej? To naj te pokesa glede tvojih služabnikov.
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Oh zgodaj nas nasiti s svojim usmiljenjem, da se bomo lahko veselili in bomo veseli vse naše dni.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Stôri nas vesele glede na dneve, v katerih si nas prizadel in leta, v katerih smo videli zlo.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Naj se tvoje delo pokaže tvojim služabnikom in tvoja slava njihovim otrokom.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
Nad nami pa naj bo lepota Gospoda, našega Boga. Utrdi delo naših rok nad nami; da, delo naših rok, utrdi ga.

< Psalms 90 >