< Psalms 90 >
1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Orazione di Mosè, uomo di Dio O SIGNORE, tu ci sei stato un abitacolo In ogni età.
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Avanti che i monti fosser nati, E che tu avessi formata la terra ed il mondo; Anzi ab eterno in eterno tu [sei] Dio.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Tu fai ritornar l'uomo in polvere, E dici: Ritornate, o figliuoli degli uomini.
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Perciocchè mille anni [sono] appo te Come il giorno d'ieri, quando è passato; O [come] una vegghia nella notte.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Tu porti via gli [uomini], come per una piena d'acque; Essi [non] sono [altro che] un sogno; Son come l'erba che si rinnovella la mattina.
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
La mattina ella fiorisce e si rinnovella; E la sera è segata e si secca.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Perciocchè noi veniam meno per la tua ira; E siam conturbati per lo tuo cruccio.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Tu metti davanti a te le nostre iniquità, [E] i nostri [peccati] occulti alla luce della tua faccia.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Conciossiachè tutti i nostri giorni dichinino per la tua ira; Noi abbiam forniti gli anni nostri [così presto] come una parola.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
I giorni de' nostri anni, in alcuni [non sono che] settant'anni; E [in altri], se ve ne sono di [maggiori] forze, [che] ottant'anni; Ed [anche] il fiore di quelli [non è altro che] travaglio e vanità; Perciocchè di subito è riciso, e noi ce ne voliam via.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Chi conosce la forza della tua ira, E la tua indegnazione, secondo che devi esser temuto?
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Insegna[ci] adunque a contare i nostri dì; Acciocchè acquistiamo un cuor savio.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Rivolgiti, Signore; infino a quando? E sii rappacificato inverso i tuoi servitori.
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Saziaci [ogni] mattina della tua benignità; Acciocchè giubiliamo, e ci rallegriamo tutti i dì nostri.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Rallegraci, al par de' giorni che tu ci hai affliti; Degli anni che abbiamo sentito il male.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Apparisca l'opera tua verso i tuoi servitori, E la tua gloria verso i lor figliuoli.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
E sia il piacevole sguardo del Signore Iddio nostro sopra noi; E addirizza, [o Signore], sopra noi l'opera delle nostre mani.