< Psalms 90 >
1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Mózesnek, az Isten emberének imádsága. Uram, te voltál nékünk hajlékunk nemzedékről nemzedékre!
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Minekelőtte hegyek lettek és föld és világ formáltaték, öröktől fogva mindörökké te vagy Isten.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Te visszatéríted a halandót a porba, és ezt mondod: Térjetek vissza embernek fiai!
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Mert ezer esztendő annyi előtted, mint a tegnapi nap, a mely elmúlt, és mint egy őrjárási idő éjjel.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Elragadod őket; olyanokká lesznek, mint az álom; mint a fű, a mely reggel sarjad;
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
Reggel virágzik és sarjad, és estvére elhervad és megszárad.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Bizony megemésztetünk a te haragod által, és a te búsulásod miatt megromlunk!
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Elédbe vetetted a mi álnokságainkat; titkos bűneinket a te orczádnak világa elé.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Bizony elmúlik minden mi napunk a te bosszúállásod miatt; megemésztjük a mi esztendeinket, mint a beszédet.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
A mi esztendeinknek napjai hetven esztendő, vagy ha feljebb, nyolczvan esztendő, és nagyobb részök nyomorúság és fáradság, a mely gyorsan tovatünik, mintha repülnénk.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Ki tudhatja a te haragodnak erejét, és a te félelmetességed szerint való bosszúállásodat?
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Taníts minket úgy számlálni napjainkat, hogy bölcs szívhez jussunk.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Térj vissza Uram! meddig késel? és könyörülj a te szolgáidon.
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Jó reggel elégíts meg minket a te kegyelmeddel, hogy örvendezzünk és vígadjunk minden mi időnkben.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Vidámíts meg minket a mi nyomorúságunk napjaihoz képest, az esztendőkhöz képest, a melyekben gonoszt láttunk.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Láttassék meg a te műved a te szolgáidon, és a te dicsőséged azoknak fiain.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
És legyen az Úrnak, a mi Istenünknek jó kedve mi rajtunk, és a mi kezünknek munkáját tedd állandóvá nékünk, és a mi kezünknek munkáját tedd állandóvá!