< Psalms 90 >
1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Ihooya rĩa Musa, ndungata ya Ngai JEHOVA, nĩwe ũtũũrĩte ũrĩ gĩikaro giitũ kuuma njiarwa na njiarwa.
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
O mbere ya irĩma kũgĩa kuo kana ũkĩũmba thĩ na mabũrũri, kuuma tene nginya tene, Wee ũrĩ o Mũrungu.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Wee ũcookagia andũ magatuĩka rũkũngũ, ũkoiga atĩrĩ, “Cookai rũkũngũ-inĩ, inyuĩ ciana ici cia andũ.”
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Nĩgũkorwo mĩaka ngiri harĩwe no ta mũthenya wa ira ũrĩa ũrahĩtũkire, kana ta ituanĩra rĩmwe rĩa arangĩri a ũtukũ.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Ũhaataga andũ, ũkameeheria, magakoma toro wa gĩkuũ; andũ mahaana ta nyeki ĩrĩa ĩringũkaga rũciinĩ:
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
o na gũtuĩka rũciinĩ nĩĩringũkaga, hwaĩ-inĩ ĩhoohaga, ĩkooma.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Tũniinagwo nĩ marakara maku, na tũkamakio mũno nĩ marũrũ maku.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Nĩũigĩte wĩhia witũ o mbere yaku, mehia maitũ marĩa mahithe ũkamoimĩria o ũtheri-inĩ hau mbere yaku.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Matukũ maitũ mothe maniinagwo nĩ mangʼũrĩ maku; tũninũkagia mĩaka iitũ na gũcaaya.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
Mũigana wa matukũ maitũ-rĩ, nĩ mĩaka mĩrongo mũgwanja, kana mĩrongo ĩnana, tũngĩkorwo tũrĩ na hinya; no rĩrĩ, mũigana wamo no thĩĩna na kĩeha, nĩgũkorwo mathiraga o narua, na ithuĩ tũgathiĩ, tũkabuĩria.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Nũũ ũũĩ hinya wa marakara maku? Nĩgũkorwo mangʼũrĩ maku nĩ manene o ta gwĩtigĩrwo kũrĩa wagĩrĩire.
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Tuonie gũtara matukũ maitũ wega, nĩgeetha tũgĩe na ngoro ya ũũgĩ.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Wee Jehova, hoorera! Nĩ nginya rĩ? Iguĩra ndungata ciaku tha.
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Rũciinĩ tũhũũnagie na wendo waku ũtathiraga, nĩguo tũinage nĩ gũkena na tũcanjamũkage matukũ maitũ mothe.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Tũma tũkene matukũ maingĩ o ta marĩa ũtũnyamarĩtie, na mĩaka mĩingĩ o ta ĩrĩa tuonete thĩĩna.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Ndungata ciaku irokĩonio ciĩko ciaku, naguo riiri waku wonio ciana ciao.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
Wega wa Mwathani Ngai witũ ũrogĩa na ithuĩ; tũma wĩra wa moko maitũ ũgaacĩre, ĩĩ-ni, kĩrũmie wĩra wa moko maitũ.