< Psalms 90 >

1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Молитва на Божия човек Моисей. Господи, Ти си бил нам обиталище из род в род,
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Преди да се родят планините, И да си дал съществувание на земята и вселената, От века и до века Ти си Бог.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Обръщаш човека на пръст, И казваш: Върнете се човешки чада.
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Защото хиляда години са пред Тебе Като вчерашния ден, който е преминал, И като нощна стража.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Като с порой ги завличаш; те стават като сън; Заран са като трева, която пораства;
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
Заран цъфти и пораства; Вечер се окосява и изсъхва.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Защото довършваме се от Твоя гняв, И от негодуванието Ти сме смутени.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Положил си беззаконията ни, пред Себе Си, Скришните ни грехове в светлината на лицето Си
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Понеже всичките ни дни преминават с гнева Ти. Свършваме годините си като въздишка.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
Дните на живота ни са естествено седемдесет години Или даже, гдето има сила, осемдесет години, Но най-добрите от тях са труд и скръб, Защото скоро прехождат и ние отлитаме.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Кой знае силата на гнева Ти И на негодуванието Ти според дължимия на Тебе страх?
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Научи ни така да броим дните си Щото да си придобием мъдро сърце.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Върни се, Господи; до кога? И дано се разкаеш за скърбите на слугите Си.
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Насити ни рано с милостта Си, За да се радваме и веселим през всичките си дни.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Развесели ни съразмерно с дните, в които си ни наскърбявал. И с годините, в които сме виждали зло.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Нека се яви Твоето дело на слугата Ти, И Твоята слава върху чадата им.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
И нека бъде върху нас благоволението на Господа нашия Бог, да ни ръководи; И утвърждавай за нас делото на ръцете ни; Да! делото на ръцете ни утвърждавай го.

< Psalms 90 >